You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Governorship Election Updates: Ẹni tí Tinubu bá padà lẹ́yìn rẹ̀, Ọlọ́run ti padà lẹ́yìn onítọ̀ún - Alátìlẹyìn Sanwo-Olu

Àáyá ti bẹ́ sílẹ̀, ó bẹ́ áré ni ọ́rọ́ ìdìbò tònìí. BBC Yorùbá yóò máa mú gbogbo ìròyìn bó ṣe ń lọ káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lórí ètò ìdìbò gómìnà àti àwọn ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ kọọkan wá fún un yín

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Busayo Akogun and Yemisi Oyedepo

  1. INEC ìpinlẹ Ekiti láwọn ti fawọn ẹrọ amunawa yanju iṣorọ ki ẹrọ kaadi idbo gbéná lọ lọjọ idibo, INEC: Ohun gbogbo la ti pése silẹ ki eto idibo le lọ daadaa ni ọla

    INEC: Ohun gbogbo la ti pése silẹ ki eto idibo Ekiti le lọ daadaa ni ọla

  2. Ọlọ́pàá kò dúnkokò mọ́ ọmọ ẹgbẹ́ PDP ní Bauchi- Ọ̀gá ọlọ́pàá, Ọ̀gá ọlọ́pàá ní ìpínlẹ̀ Bauchi, Ali Janga irọ́ ní àwọn agbófinró kò dúnkokò mọ́ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú alátakò ní ìpínlẹ̀ náà

    Ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ní ní ìpínlẹ̀ Bauchi sọ pé irọ́ ni ìròyìn tó sọ pé àwọn mú ọmọ ẹgbẹ́ PDP bí ọ̀dúnrún ún

  3. Alága ajo eleto idibo ni ilu Ijebu Ode, Ogbeni Kayode Olaniyi ni ko sohun kankan to sẹku to yẹ kí INEC ṣe tí wọn ko tii ṣe., Gege bí alabojuto ajo INEC to wá ní Ijebu Ode Ogbeni Kayode Olaniyi ṣe sọ ó, "gbogbo nkan elo lọ tí wá ní digbi".

    O ni Gbogbo ohun èlò lo tí wá nikalẹ fún ìdìbò woorowo tí wọn sì ti kó àwọn ohun elo náà lelekunjekun àti iye oludibo to forúkọ sílè lọ sí ibùdó idibo. Gbogbo ìwé itekasi, káàdì tí yóò ṣe aridaju oludibo.

    O ni àwọn iwe ti wọn yoo ko esi ibo si àtàwọn ohun elo elege lo tí wa larowoto àwọn osise tí yóò lo wọn.

  4. Ìdìbò ọjọ́ Sátidé kò dí ayẹyẹ àyájọ́ ọjọ́ obìnrin lágbàáyé lọ́wọ́ ní ìlú Port Harcourt, Àwọn obìnrin ní ìpínlẹ̀ Rivers tú yáyá jáde fún àyájọ́ ọjọ́ obìnrin ní ìpínlẹ̀ Rivers

    Ìpalẹ̀mọ́ ìdìbò gómìnà kò dí àwọn obìnrin lọ́wọ́ lẹ́yìn tí wọ́n jáde lọ́mọde lágbà nílùú Port Harcourt fún àyájọ́ ọjọ́ obìnrin lágbàáyé

  5. Àjọ INEC ìpínlẹ̀ Edo ti n pín ohun eelo ìdìbò kaakiri ẹka mẹrinlelogun ti idibo a ti waye lọla

    INEC Edo ni ọwọ wọn ti tẹ ohun gbogbo ti wọn nilo lati ṣeto idibo alaṣeyọri bayii

  6. Àwọn obìnrin fẹ̀họ́nú hàn lórí báwọn ologun ṣe yabo ààfin ọba wọn ni Okochiri ní ìpínlẹ̀ Rivers, Ọ̀gọ̀rọ̀ àwọn obìnrin àti ọ̀dọ́ ni wọ́n fi ìbímú jáde tí wọ́n sì ń fẹ̀họ́nú ní ìjọba ìbílẹ̀ Okirika ní ìpínlẹ̀ Rivers

    Ọjọ́bọ̀ ọjọ́ kèje oṣù kẹ̀ta ni àwọn sọ́jà yabo ààfin ọba Ateke Tom Amanyanabo ti ìlú Okochiri.

  7. Imaamu Nanzif Inuwa to ṣáájú ìrun ní Kano rọ àwọn oludibo lati fi sùúrù yan ẹni to wù wọn sipò lọ́la, Imam na tun gbadura pé idibo ọla kò ni la ẹmi lọ

    Imam Nazifi Inuwa ni àsìkò ti to ki àwọn eniyan Kano yan ẹni to maa tun ipinlẹ náà ṣe.

  8. Ganduje ní òun yóò gba èsì yóòwù tó bá jáde ní ìdìbò gómìnà Kano, Gomina ipinlẹ Kano ni oun a gba kadara lori èsì ìdìbò ọla

    2019 elections: Ganduje ní òun yóò gba èsì yóòwù tó bá jáde ní ìdìbò gómìnà Kano

  9. Awara Biokpomabo to jẹ oludije ẹgbẹ oṣelu AAC ni Rivers ti kéde ará rẹ gẹgẹ bi oludije lẹgbe APC, O ni koda ẹgbẹ oṣelu YPP ti gba oun wole pẹlu lati ṣoju Rivers

    Awara ti ẹgbẹ African Action Congress sọ fun BBC pe otitọ ni pe ẹgbẹ All Progressives Congress ti gba oun gẹgẹ bii ẹni ti yoo dije dupo gpomina fun wọn lọla.

  10. Ìmáàmù rọ àwọn olùdìbò pé kí wọ́n gbowó lọ́wọ́ olóṣèlú ṣùgbọ́n kí wọ́n dìbò fẹ́ni tó wù wọ́n, Ìmáàmù Agunbiade ní Ilorin pọ̀rọwà fáwọn eèyàn kí wọ́n lọ tẹ̀ka lọ́jọ́ Sátidé

    Ni mọṣalaṣi ni agbegbe Saw Mail ni Ilọrin ni o ti gbamọran yii

  11. Ẹrọ to n ka kaadi ni onikaluku a lò fi dibo gomina, Alaga ajọ eleto idibo ti ni idibo ti ẹrọ kaadi idbo ba kà nikan ni wọn yoop gba wọle

    Ẹrọ to n ka kaadi ni onikaluku a lò fi dibo gomina

  12. Kò sí rínrìn kiri láti aago méjìlá ọjọ Eti si aago mẹfa ọjọ Abamẹta ni Rivers, Agbofinro mẹta a wà ni ibudo idibo kọọkan nipinlẹ Rivers

    Ibudo idibo 4442 ni wọn ti maa dibo ni ipinlẹ Rivers, Usman Belel to jẹ adari awọn eleto aabo ni ko ni si ijade ati iwọle lati aago mejila oru ọjọ Eti si aago mẹfa irọle ọjọ Abamẹta

  13. Érọ aṣe àyẹwò kaadi idibo ti wa ni kalẹ̀ ni Ipokia bákan náà ni ni Ekiti, Érọ aṣe àyẹwò kaadi idibo àti àwọn eroja míraǹ ti wa nílẹ ni ijoba ibile Ipokia

  14. Garba Lawal to n tukọ ajọ INEC Kano ni wọn ti pin ohun eelo idibo tan ni Kano, O ni alẹ ana, ọjọ alamisi ni INEC Kano ti pin gbogbo ohun eelo kaakiri ijọba ibilẹ mẹrinlelogoji Kano bi o ti yẹ

    Garba ni INEC ipinlẹ Kano ti ṣetan lati ṣeto idibo to yaranti

  15. Iṣẹ́ ti bẹ̀rẹ̀ nipinlẹ Kebbi, Wọn ti n pin ohun eelo idibo kaakiri ijọba ibilẹ Kebbi

    Awọn ọkọ agbopfinro ni wọn fi n ko awọn eelo idibo naa lati ibikan lọ si ikeji

  16. Alaga ajọ INEC ni Zamfara ti n bá àwọn aṣojú ẹgbẹ́ òṣèlú sọ̀rọ̀, Arabinrin Asmau Sani Maikudi n ba àwọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu sọrọ alaafia ni Zamfara

    Arabinrin Asmau Sani Maikudi n ba àwọn aṣoju ẹgbẹ oṣelu sọrọ alaafia ni Zamfara

  17. Gomina Godwin Obaseki ti ipinlẹ Edo ṣe ìpàdé alaafia pẹ̀lú àwọn oṣiṣẹ, Gomina ni òun pé ìpadé yii láti fàwọn oṣiṣẹ Edo lọkan balẹ̀ ṣaaju idibo

    Gomina ni òun pé ìpadé yii láti fàwọn oṣiṣẹ Edo lọkan balẹ̀ ṣaaju idibo

  18. Bayii ni wọ́n ṣe n pín ohun eèlò ìdìbò fun ijọba ibilẹ ogún nipinlẹ Bauchi

    Wọn ti n pin ohun eelo idibo kaakiri ipinlẹ Bauchi ni ẹ̀ka banki Naijiria to wa ni Bauchi.

  19. Àwọn jàǹdùkú dáná sun ọ́ọ̀físì INEC ní Akwa-Ibom

      • Author, Moseph Ekine
      • Role, Broadcast Journalist Pidgin

    Awọn janduku ti dana sun ọọfisi ajọ INEC to wa ni ijọba ibilẹ Ibesikpo Asutan nipinlẹ Akwa Ibom.

    Botilẹjẹ wi pe ko ti i si ẹni to mọ nkan to fa ijamba naa, alaga ajọ INEC nipinlẹ naa, Mike Igini ti ṣabẹwo si agbegbe naa lati wo bi ile naa ṣe jona si, tabi boya o jo awọn nkan idibo.

    Ibẹru-bojo wa ni ipinlẹ Akwa Ibom ṣaaju ki eto idibo gomina to o waye.

    Gomina Udom Emmanuel naa n dije fun saa keji.

  20. L'ákọ ni àwọn apẹja àtàwọn tó ń wa iyanrìn wà fún ìdìbò ní Benue

      • Author, Dooshima Abu
      • Role, Benue, Nigeria

    Awọn apẹja ati awọn to n wa erupẹ nipinlẹ Benue sọ pe awọn ti gbaradi fun idibo ti yoo waye lọjọ Abamẹta.

    Diẹ lara wọn to ba akọroyin BBC sọrọ sọ pe awọn fẹ ẹ dibo yan olori ti yoo pese iṣẹ fun awọn, ati ileewe f’awn ọmọ wọn.