You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Governorship Election Updates: Ẹni tí Tinubu bá padà lẹ́yìn rẹ̀, Ọlọ́run ti padà lẹ́yìn onítọ̀ún - Alátìlẹyìn Sanwo-Olu

Àáyá ti bẹ́ sílẹ̀, ó bẹ́ áré ni ọ́rọ́ ìdìbò tònìí. BBC Yorùbá yóò máa mú gbogbo ìròyìn bó ṣe ń lọ káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lórí ètò ìdìbò gómìnà àti àwọn ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ kọọkan wá fún un yín

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Busayo Akogun and Yemisi Oyedepo

  1. Gomina Ibikunle Amosun tipinlẹ Ogun ti dibo

    Ibikunle Amosun n ṣatilẹyin fun Akinlade ti ẹgbẹ oṣelu APM dipo APC ti oun ba jade

  2. Adebayọ Adelabu dìbò ní Ibadan

      • Author, Adedayo Okedare
      • Role, BBC Yoruba
  3. Sharafadeen Alli tó tò sẹyin oludije ẹgbẹ PDP ti dibo

    Oludije ZLP tẹlẹ nipinlẹ Ọyọ, Sharafadeen Alli ti dibo bayii.

  4. Olóṣèlú tó n pín owó gbá akọ̀ròyìn BBC létí nípínlẹ̀ Eko

    Ṣegun Adewale ti Aeroland gbá akọroyin BBC léti nitoripe o n ká fidio bi o ṣe n pín ẹgbẹrun kan naira fun awọn oludibo ni Pleasure bus stop nipinlẹ Eko.

  5. Faṣọla dibo nilu Eko

  6. Arugbo ti ọmọ rẹ pọn sẹyin lọ dibo

  7. Adegbenga Kaka dibo ni woodu Kashamu

      • Author, Yetunde Olugbenga
  8. Adeleke ni sọ fun BBC pé o da oun loju pe oun a bori nile ẹjọ

    Ademola Adeleke to dije dupo gomina nipinlẹ Osun ni oun yoo bori nile ẹjọ laipẹ

  9. Ibudo idibo Akeredolu ni ipinlẹ Ondo ni yii ti o da

    Awọn eniyan ibudo idibo wọọdu yii ko pọ to

  10. Ọwọ́ EFCC tún tẹ apò owó 'fún ìbó rírá' ní Benue

    Ajọ EFCC, sọ pe niṣe ni awọn janduku kọlu awọn oṣiṣẹ ajọ naa to n gbiyanju lati fi panpẹ mu ẹni to fẹ ẹ pin owo naa, ti wọn si tun ba ọkọ ajọ naa jẹ.

    Agbegbe North Bank nilu Makurdi ni ọwọ ti tẹ ẹ.

  11. Ṣeyi Makinde, olùdíje gómìnà ní ìpínlẹ̀ Ọyọ dìbò

  12. Gomina Ambode ti dibo ni wọọdu rẹ ni Ẹpẹ

    Gomina Ambode to jẹ ọkan lara awọn gomina ti ko ni pada wa fun saa keji ni o ti dibo bayii ni ilu epe ni ipinlẹ Eko

    Babajide Sanwo Olu lo n dije dupo gomina ipinle Eko lẹgbe oṣelu APC

  13. Lai Mohammed dìbò ní ìlú Òró ní Kwara

    Minisita fún ètò ìròyìn àti Ásà, Alhaji Lai Muhammed dibò ní Polling unit 006, Oro ward 2, Irepodun LG, Kwara.

  14. Ọwọ́ tẹ ọkùnrin kan tó n pín owó níbùdò ìdìbò ní Kwara

    Ọwọ awọn oṣiṣẹ ajọ to n gbogun ti iwa ibajẹ ni Naijiria, EFCC, tẹ arakunrin kan Abdulkareem Abdulsalem, to n pin owo fun awọn oludibo nilu Ilọrin.

    Ninu iroyin kan ti ajọ naa fi sita loju opo Twitter rẹ, EFCC sọ pe ni ẹka ibudo idibo keje ni ileewe awọn olukọni, Kwara State College of Education, ni ọwọ ti tẹ ọkunrin naa

  15. Alao Akala dìbò nílù Ogbomọṣọ

    Gomina nigba kan fun ipinlẹ Ọyọ, to tun jẹ oludije fun ipo gomina ninu ẹgbẹ oṣelu Action Democratic Party, ADP, ko to o di pe o wọgile ipinnu rẹ naa tibo nilu Ogbomọṣọ pẹlu aya rẹ, Kẹmi Alao-Akala.

  16. Àwọn àkàndá ẹ̀dá náà jáde láti dìbò ní Ẹdẹ

  17. Kí ló fà á tí kọmísánà ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Edo bínú lásìkò ìdìbò?

      • Author, Onyinye Chime
      • Role, BBC Pidgin, Lagos

    Iṣẹ igbọnsẹ, a kii fi ran ọmọ. Funra kọmisana ọlọpaa nipinlẹ Edo, Danmallam Mohammed, lo bọ si oju ọna lati gbe nkan di ojupopo.

    Botilẹjẹ wi pe ko yẹ ko si igboke-gbodo kankan nitori idibo, niṣe ni awọn olugbe ilu Benin n ṣe ohun to kan kaluku wọn bi ẹni pe ko si idibo.

    Awọn ọlọkọ eero ati aladani n lọ, ti wọn si n bọ lojupopo. Eyi lo mu ki inu bi kọmisana ọlọpaa naa, to si bọ si oju ọna lati gbofinro funra rẹ.

  18. Wàhálà bẹ́ sílẹ̀ ní àgọ́ ìdìbò Ademọla Adeleke

  19. ''L'ákọ ni mo sì wà fún ìdíje gómìnà''

    Oludije fun ipo gomina ninu ẹgbẹ oṣelu Action Alliance, AA, Uche Nwosu ti pariwo sita pe irọ ni irpyin kan to sọ pe oun ti yọwọ ninu idije fun ipo gomina ipinlẹ Imo.

    Nwosu to jẹ ọkọ ọmọ gomina ipinlẹ naa lọwọlọwọ, Rochas Okorocha, sọ pe awọn alatako oun lo wa nidi iroyin naa.

  20. Gómìnà Abdulfatai Ahmed dìbò ní Kwara