You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Governorship Election Updates: Ẹni tí Tinubu bá padà lẹ́yìn rẹ̀, Ọlọ́run ti padà lẹ́yìn onítọ̀ún - Alátìlẹyìn Sanwo-Olu

Àáyá ti bẹ́ sílẹ̀, ó bẹ́ áré ni ọ́rọ́ ìdìbò tònìí. BBC Yorùbá yóò máa mú gbogbo ìròyìn bó ṣe ń lọ káàkiri orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lórí ètò ìdìbò gómìnà àti àwọn ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ìpínlẹ̀ kọọkan wá fún un yín

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Busayo Akogun and Yemisi Oyedepo

  1. Kọmísánà ọlọ́pàá tuntun gúnlẹ̀ sí Bayelsa fún ìdìbò, Ko ni i si idibo gomina ni Bayelsa

      • Author, Gift Andrew
      • Role, BBC Pidgin Reporter, Bayelsa State

    Kọmisana ọlọpaa mi i ti gunlẹ si ipinlẹ Bayelsa.

    Shọla David ni yoo mojuto eto idibo ile igbimọ asọfin ipinlẹ naa.

    David n rọpo Aminu Pai Saleh to mojuto eto idibo aarẹ nipinlẹ Bayelsa.

    Ijọba ibilẹ mẹjọ ni wọn yoo ti dibo to ni ẹka mérinlelogun

  2. Àjọ ọlọpàá ìpínlẹ̀ Ọyọ àti Kwara ṣe ìpá́dé̀ pẹ̀lú àwọn tọ́rọ̀kan, Egbetokun tó bá àwọn oniroyin sọ ro n'ilu Ilorin ni àjo Ọlọpa àti gbogbo eso abo tí gbaradi

    Àwọn ọlọpàá ní ìpínlẹ̀ ọyọ́ ṣe ìpàdé àpérò pẹ̀lú àwọn tọ́rọ̀kàn nibi ètò ààbò ní olú ilé iṣẹ́ ọlọpàá ní Ibadan.

    Lára àwọn tó pẹ́ju síbẹ̀ ní asojú DSS, FRSC, NSCDC, àwọn ọga aṣọ́bode àti àwọn akọròyìn.

    Èrèdí ìpàdé ọ̀hún ni láti ṣe ìlanilọ́yẹ fún àwọn olùdibò àti àwọn elétò ààbò sáájú ìdìbò tí yóò wáyé lọ́jọ́ Àbámẹ́ta.

    Bákan náà ní Ìpinlẹ Kwara

    Komisana Ọlọpa ní Ìpínlẹ̀ Kwara, Kayode Egbetokun ní Ọkọ baalu àwọn ọmọ ajọ ológun yóò máa yi de kí rí ní Satide ọjọ́ idibò di pò baalu helicopter tí wọn fí yi de lọ́jọ́ ìdìbò aare ní Ìpínlẹ̀ Kwara.

    Egbetokun tó bá àwọn oniroyin sọ ro n'ilu Ilorin ni àjo Ọlọpa àti gbogbo eso abo tí gbaradi láti rí pé eto ìdìbò ọjọ́ Satide wáyé ní ìró wo rò ṣe lábẹ́ ààbò tó gbó pọ.

    O ni gbogbo ètò ló tí tó láti rí pé eto ìdìbò náà wáyé ní abẹ àbò tó gbó pọn. Egbetokun ní gbogbo eso abo àti àwọn ológun tí yóò kó pá nínú ètò ìdíbo náà ni wọ́n ti gbà idani leko tó pé.

  3. Àwọn oludije 2,134 lo n dije dupo gomina ni Naijiria lọjọ Abamẹta

    Ipinlẹ mọkandinlọgbọn ni wọn yoo ti yan gomina tuntun lọjọ Abamẹta.

  4. Gomina Ahmed kìlọ̀ fún àwọn jàǹdukú láti jìnà sí ìpínlẹ̀ Kwara

    Gómínà ìpínlẹ̀ Kwara, Abdulfatah Ahmed tí fi ikilọ síta fún àwọn jan duku àti ada rugudu silẹ láti jìnnà réré sí Ìpínlẹ̀ náà ṣáájú lásìkò àti lẹ́yìn ìdìbò.

    Ahmed ṣe ikilọ náà ní gbà ti o nse ìpàdé pẹ̀lú àwọn olórí òṣìṣẹ́ abo ní Ìpínlẹ̀ Kwara.

    Ó ní àwọn agbofinro yóò fi ìyà tó tọ́ jẹ ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ dá rukérúdó sílẹ̀ lásìkò ètò idibò.

  5. Alága ìjọba ìbílẹ̀ mẹfa ati kanselọ mejilelọgọta ni wọn yoo dibo yan ni FCT, Awọn ẹẹyan Abuja yoo yan alaga ijọba ibilẹ mẹfa lọjọ Abamẹta

    Kuje, Gwagwalada, Kwali, Sheda aarin gbungbun Municipal, Bwari yoo yan alaga tuntun

  6. Sùpàgẹ́tì, ṣúgà àti kẹrosínì l'àwọn olóṣèlú n pín ṣáàjú ìdìbò

    Niṣe ni awọn eniyan kan to bẹẹrẹ ni olu ile ẹgbẹ oṣelu APC to wa ni Makurdi, olu ilu ipinlẹ Benue, lati gba supagẹti, ati ṣuga.

    Àná ni ẹgbẹ naa bẹrẹ si ni pin in.

    Bakan naa ni awọn kan n gba epo oyinbo ni ipinlẹ Abia.

  7. INEC ti n pín àwọn ohun èlò ìdìbò ní ìpínlẹ̀ Kwara

    Àjọ èlétó idibo Nàìjíríà ti bẹ̀rẹ̀ gbígbé àwọn ohun èlò tó se kókó lọ sí tibu tóóró Ìpínlẹ̀ Kwara.

    Pínpín ohun èlò náà bẹ̀rẹ̀ ní Ọjọ́ru níí bánkì àpapọ̀ tó wà ní ìlú Ilorin.

    Ọ̀ga agba àjọ eleto ìdìbò ìpínlè Kwara tó ṣe àmójútó bí wọ́n ṣe pin , Mallam Attahiru Madami sọ pé ajọ náà gùn lè pínpín náà láti rí pé àwọn ohun èlò náà tètè dé ìjọba ìbílè mẹ́rìndínlógún tó wà ní Kwara.

    Madami ní ẹ̀ṣọ́ aláàbò tó dìhámọ́ra ogun mẹwa-mẹwa ní yí o tẹ̀lé ọkọ̀ kọ̀ọ̀kan tí ó ń gbé àwọn ohun èlò ìdìbò.

  8. Kò sí ìwé ẹ̀rí fun olùdíje tí tó ba wóle lábẹ hílàhílo

    Àjọ elétò ìdìbò Nàìjíríà (INEC) ti ni kò sí ìwé ẹ̀rí fun olùdíje kankan tí ó ba jáwé olúbori lábẹ ìdìbo to ní hílàhílo.

    O tun ni ajọ naa ko ni pin iwe ẹri fun ẹnikẹni to ba jawe olubori lasiko ti òṣìṣẹ́ eléto ìdìbò ba sọ èsì ìdìbò nítori pé ẹ̀mi rẹ̀ wà lábẹ́ ewu nínú níbi ìdìbò gómìnà tí yóò wáye lọ́la Satide, ọjọ kẹsàn osù Kẹ́ta, ọdún 2019.

    Bákaǹ náà ni àjọ náà fi kún pé gbogbo ibi tí òṣìṣẹ́ INEC bá ti mọ̀ọ́mọ̀ maa lo ẹ̀rọ ayẹ káàdì ìdìbò wò ní àwọn yóò wọ́gilé ìdìbò wọn.