You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Ọ̀pọ̀ èèyàn di àwátì lẹ́yìn tí ọkọ̀ ojú omi ńlá kọlù afárá l’Amẹrika

Akojọpọ awọn iṣẹlẹ kaakiri agbaye

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Olumide Owaduge and Olubusola Afolayan

  1. Akọ́nimọ̀ọ́gbá Adegboye Onigbinde di agbẹnusọ fún àwọn àgbàìlẹ̀ Yorùbá

    Ẹgbẹ igbimọ awọn agba ilẹYoruba ti yan akọnimọọgba awọn agbabọọlu orilẹ-ede yii nigbakanri Oloye Adegboye Onigbinde gẹgẹ bi aṣoju igbimọ agba ilẹ Yoruba.

    Dokita Victor Taiwo ẹni ti o pe ipade awọn agba Yoruba ni, asiko ti to fun iran Yoruba lati fohun kan sọrọ.

    Ipade naa lo waye ninu gbagede awọn lọba lọba to waye ninu ọfiisi ipinlẹ Oyo.

    Taiwo ni ija to wa laarin awọn agba to n ṣoju ilẹ Yoruba lọ fa idi ti olori tuntun fi gbọdọ wa.

    Taiwo ninu ọrọ rẹ ṣalaye wi pe "ti wọn ba ni ki ẹgbẹ Yoruba mu aṣoju iran Yoruba kan wa ẹgbẹ wo ló fẹ ran eeyan lọ, ṣe ẹgbẹ afenifere ni, ṣe afenifere Ayo Adebanjo ni? abi ti Fasoranti, abi ti Ayo Fasanmi ewo nibẹ?

    Idi niyi ti a fi nilo lati yan aṣoju tuntun fun ilẹ Yoruba ti kii ṣe oloṣelu to si jẹ oloootọ, to nifẹ iran Yoruba.

    Taiwo ni pẹlu igbesẹ yii aaye wa fun awọn igun Yoruba miran lati darapọ mọ ẹgbẹ agba ilẹ Yoruba tuntun kí iran Yoruba le fi ohun kan sọrọ".

    Ninu ọrọ rẹ oloye Adegboye Onigbinde ni iṣẹ tuntun ni iran Yoruba gbe le oun lọwọ gẹgẹ bi aṣoju agba ile Yoruba ti oun yoo fi gbogbo agbara ṣe.

    Akọnimọọgba awọn agbabọọlu orilẹ-ede yii nigbakanri tẹ siwaju ninu ọrọ rẹ wi pe "ilẹ Yoruba ti jẹ ọpọlọpọ iya latẹyin wa, mi o fẹ ki awọn ọmọ mi ati awọn ọmọ rẹ jẹ iru iya bẹẹ.

    Oun ti a o kọkọ ṣe ni wi pe a o wa ọna ti ẹnu wa yoo ṣe ko, to fi jẹ wipe ibi ti a ba nlọ ni ao maa wi pe a nlọ."

    Onigbinde jẹjẹ wipe oun ko ni fi oṣelu ṣe iṣakoso ki idagbasoke le ba iran Yoruba, nitori ẹbun pọ lara awọn ọdọ Yoruba.

    Lara awọn to peju sinu Ipade naa ni Erelu Abiola Dosunmu Yeye Oba ti Ile Ife ti wọn yan gẹgẹ bi igbakeji oloye Onigbinde, Ọba Micheal Odunayo Ajayi, Arowotawaya Ẹlerinmo ti Erinmo Ijesha, Aṣoju Olubadan ti ilẹ Ibadan Ọba Mamhood Olalekan Balogun, atawọn aṣoju ẹgbẹ ilẹ Yoruba.

  2. Ta ni Àmbásádọ̀ Sarafa Tunji Ishola, Aṣojú Nàìjíríà ní UK tí Ààrẹ Tinubu pàṣẹ pé iṣẹ́ rẹ̀ tó gẹ́ lẹ́yìn ọdún méjì tí Buhari yàn án?

  3. Wo bí àwọn èèyàn ṣe ń fi ẹ̀rin ṣe eré ìdárayá

  4. NLC kéde Ìyanṣẹ́lódì ọjọ́ méjì lórí owó ìrànwọ́ epo

  5. Kí ló fa 'gbas gbos' láàárín àwọn káńsílọ̀ àti alága ìjọba ìbílẹ̀ Ijebu East tí wọ́n fi ní kó lọ rọ́kún nílé

  6. Àwọn Baálẹ̀ tí wọ́n gba ìgbèga sí ipò Ọba yóò gba adé lóníì nílẹ̀ Ibadan

  7. ‘Mi ò lè ya ìgbẹ́ bìi ti tẹ́lẹ̀ mọ́ láti ìgbà tí wọ́n fi kún iye owó tí à ń san ní yàrá ìgbọ̀nsẹ̀ ìtagbangba’

  8. Ta ni Ọ̀gágun Brice Oligui Nguema adári tí ológun Gabon gbé ìjọba fún báyìí?

  9. Pínpín ìrẹ̀sì “palliative” bẹ̀rẹ̀ ní Osun

  10. Ajá pa ọmọ ìkókó, ṣe ìyá léṣe ní Ìpínlẹ̀ Osun

  11. Wo àwọn orílẹ̀ èdè tí ààrẹ wọn ti lo kọjá ọgbọ̀n ọdún nípò

  12. Pa Taiwo Akinkunmi tó ya Àsìá Nàìjíríà dágbére fáyé lẹ́ni ọdún 87!

  13. Nibo gan ni Ali Bongo wa? – “A ti sé e m’ọ́lé!”

    Aarẹ orilẹede Gabon, Ali Bongo Ondimba to kuro lori ijọba ti wa ni isemọle bayii, ileeṣẹ iroyin AFP ni awọn ologun lo sọ bẹẹ.

    “Aarẹ Ali Bongo wa ni isemọle ti awọn mọlẹbi rẹ atawọn dokita si yi i ka,” wọn sọ eyi ninu atẹjade kan ti wọn ka jade lori ẹrọ amohunmaworan.

    Ọkan lara awọn ọmọkunrin aarẹ naa ti ko si gbaga awọn agbofinro fun ẹsun “dida alafia ru”, atẹjade naa fi kun un bẹẹ si ni ile iṣẹ iroyin Gabon 24 naa sọ bẹẹ. Ṣaaju ni awọn ologun ti farahan lori Tẹlifisan lati kede pe awọn ti gba ijọba.

    Awọn ologun naa kede pe awọn ti wọgile esi idibo to jade lọjọ Abamẹta ti ajọ eleto idibo kede Ọgbẹni Bongo gẹgẹ bi ajawe olubori. Ẹwẹ, agbẹnusọ ileeṣẹ to n ri si ọrọ ilẹ okere lorilẹede China ti pe fun aabo to daju fun ọgbẹni Bongo.

    Bakan naa ni Wang Wenbin tun rọ gbogbo awọn ti ọrọ kan lati ni ijiroro “ki wọn lee mu ohun gbogbo pada sipo laipẹ”.

  14. Èèyàn méjì lọ ṣọ́ọ̀ṣì, wọ́n rì sínú odò ní ìpínlẹ Ogun

  15. Ẹgbẹ́ òṣèlú NNPP fòfin de Kwankwaso àti àwọn míì fún oṣù mẹ́fà

  16. Ọlọ́pàá nawọ́ gán afurasí 100 níbi ìgbéyàwó akọsákọ ní ilé ìtúra kan

  17. Irinṣẹ́ tó ń darí ọkọ̀ bàálù nínú afẹ́fẹ́ dẹnukọlẹ̀! Àwọn iléeṣẹ ọkọ òfurufú kìlọ̀

    Ẹgbẹgbẹrun awọn arinrinajo oju ofurufu lo ti n ni idaduro asiko to jẹ ki wọn rinrinajo tabi ki wọn tilẹ wọgile irinajo wọn lẹyin ti iṣoro kan suyọ ninu afẹfẹ nilẹ UK.

    Ṣe ni awọn eeyan kan ha si papakọ ofurufu ni UK ati lawọn ilẹ okere rẹ, lẹyin ti ajọ to n boju to igbokegbodo awọn baalu kede adinku si iye awọn ọkọ baalu ti yoo ba si papakọ ofurufu.

    Bo tilẹ jẹ pe wọn yanju iṣoro naa, awọn alaṣẹ ni idaduro yoo ṣi wa.

    Arabinrin kan sọ fun ikọ iroyin BBC pe irinajo oun to yẹ ko jẹ ọsan yoo di ọganjọ oru bayii.

    Ikilọ ti wa jade pe idiwọ lee waye fun ọpọlọpọ ọjọ.

    Papakọ ofurufu Heathrow sọ ni ọjọ Aje pe awọn akọsilẹ to ti wa nilẹ yoo daru wọn si tun fi kun un pe awọn eeyan to fẹ rinrinajo ni Ọjọ Iṣẹgun ki wọn tete kan si ileeṣẹ ọkọ ofurufu ti wọn yan lati wadii ki wọn to morile papakọ ofurufu.

    Bakan naa, papakọ ofurufu ti London Luton jẹ ko di mimọ pe irinajo ofurufu jakejado UK yoo wa ni idaduro na tabi wiwọgile e ti wọn si ni ki awn eeyan kan si ileeṣẹ ọkọ baalu ti wọn ba fẹ ba rin lati mọ ipo ti irinajo wọn wa lọwọlọwọ.

    Ajọ alamojuto naa, Nats fi aridaju han ni irọlẹ Ọjọ Aje ki wọn to kede ni nnkan bii ago mẹta kọja iṣẹju mẹẹdogun wipe awọn ti ri iṣoro to yọju bẹẹ si ni wọn ti yanju rẹ amọ o ni “yoo to igba diẹ ki irinajo ofurufu to le pada si bo ṣe wa tẹlẹ”.

    Ọpọlọpọ Papakọ ofurufu ni UK atawọn ileeṣẹ ọkọ ofurufu to fi mọ British Airways, Virgin Atlantic ati TUI naa fara kasa idaduro ati iwọgile irinajo lọjọ Aje.

    “Awọn ileeṣẹ ọkọ ofurufu yoo ni ipenija ati ọpọ iṣẹ lati ṣe bayii. Latori mimojuto awọn arinrinajo wọn ati dida ọkọ baalu wọn pada si ilana ati aato ti wọn maa n tẹle tẹlẹ.” Oṣoṣẹ kan sọ fun BBC.

  18. Ọlọ́pàá Ilorin bẹ̀rẹ̀ sí ní wá Ọkùnrin tó pe ara rẹ̀ ní Alfa tó ń dúnkokò mọ́ oníṣòwò kan

  19. Ẹ wá gbọ́ iye ọjọ́ tí ó ṣeéṣe kí omíyalé àgbàrá ya ṣọ́ọ̀bù ṣọṣẹ́ láwọn ìpínlẹ̀ - Ìjọba kéde

  20. Igbó orò ni wọ́n sin òkú pásítọ̀ tó pa ara rẹ̀ torí olólùfẹ́ rẹ̀ sí