You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Ọ̀pọ̀ èèyàn di àwátì lẹ́yìn tí ọkọ̀ ojú omi ńlá kọlù afárá l’Amẹrika

Akojọpọ awọn iṣẹlẹ kaakiri agbaye

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Olumide Owaduge and Olubusola Afolayan

  1. Obi ati Atiku ń gbé ìdájọ́ ilé ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn lórí èsì ìbò ààrẹ lọ ilé ẹjọ́ tó ga jùlọ

    Ẹgbẹ oselu PDP ati APC ti fesi lori idajọ ti ile ẹjọ Kotẹmilọrun gbe kalẹ lọjọru lori esi ibo aarẹ to kọja lorilẹede Naijiria.

    Ile ẹjọ kotẹmilrun naa lo dajọ ni Ọjọru pe aarẹ Bola Tinubu tẹgbẹ oselu APC lo jawe olubori nitootọ ninu ibo aarẹ naa, gẹgẹ bi ajọ INEC ti kede rẹ.

    Nibayii Atiku Abubakar, tii se oludije fẹgbẹ oselu PDP ninu ibo aarẹ to kọja ti wa fesi pe oun ko fara mọ idajọ ile ẹjọ kotẹmilọrun naa.

    Bakan naa ni akẹẹgbẹ rẹ fẹgbẹ oselu Labour, Peter Obi ti salaye pe idajọ naa ko jẹ itẹwọgba lọdọ oun.

    Awọn oludije mejeeji naa, to wọ ẹgbẹ oselu APC ati ajọ eleto idibo INEC lọ sile ẹjọ lori esi ibo naa, ti wa leri leka pe awọn n gba ile ẹjọ to ga julọ ni Naijiria lọ lati yanju ọrọ naa.

    Ni klete lẹyin ti ileẹjọ giga naa gbe idajọ rẹ kalẹ lawn oludije mejeeji ọhun sọ ero wọn pe ile ẹjọ to ga julọ ya.

    Agbẹjọro fun ikọ Atiku, Oloye Chris Uche, lasiko idajọ ileẹjọ to ga julọ naa wa n rọ ileẹjọ ọhun lati se ẹda iwe idajọ naa fun oun, ki onibara oun le ni ẹtọ lati ta ko o.

    O salaye pe Atiku, tii seigbakeji aarẹ tẹlẹ ti pasẹ fun oun pe ki oun tete lọ pe ẹjọ kotẹmilọrun tako idajọ naa nile ẹjọ to ga julọ.

    Uche wa n kọminu pe ki lo de ti ile ẹjọ to ga julọ ọhun, to faake kọri lati gba kawọn akọroyin laaye lati gbe bi igbẹjọ se n l lọwọ sita, wa pada gba pe ki wọn ka idajọ wọn bo se n lọ lọwọ.

    Bakan naa ni agba amofin Livy Uzoukwu to n lewaju ikọ agbẹjọro fun Peter Obi ati ẹgbẹ oselu Labour naa ti fidi rẹ mulẹ fawọn akọroyin pe onibara oun ti pasẹ pe ki oun gbe ẹjọ naa lọ sile ẹjọ to ga julọ nilẹ wa.

  2. Wo kókó ìgbésẹ̀ 13 tí Tinubu gbé láàrin ọgọ́rùn-ùn ọjọ́ tó di ààrẹ

  3. Ilé ẹjọ́ fi òǹtẹ̀ lù àṣeyọrí Bola Tinubu ní ìdìbò ààrẹ

  4. Labour Party yarí, wọ́n ní àwọn kò gba ìdájọ́ Tribunal wọlé

    Ẹgbẹ oṣelu Labour Party ti ni awọn ko ni tẹwọgba idajọ ti ile ẹjọ gbe kalẹ lori ẹjọ ti wọn fi tako iyansipo Aarẹ Bola Tinubu ti ẹgbẹ oṣelu APC.

    Igbimọ onidajọ ti Adajọ Haruna Tsammani lewaju wọgile ipe ẹgbẹ oṣelu Labour Party, to si ni ko lẹsẹ nilẹ rara.

    Ninu atẹjade ti Ẹgbẹ oṣelu Labour fi ransẹ si awọn akọroyin niluu Abuja ,Akọwe ẹgbẹ, Obiora Ifoh bura pe ẹgbẹ oṣelu Labour ko ni gba esi idajọ naa wọle.

    O wa rọ gbogbo awọn alatilẹyin ẹgbẹ naa lati ṣe suru nitori awọn ko ti jawọ.

    Ifoh ni ẹgbẹ yo bawọn agbẹjọro sọrọ lati mọ igbesẹ to kan lati gbe ti awọn yo fi ri idajọ ododo gba.

    “Ẹgbẹ oṣelu Labour Party wo bi nikan ṣe lọ pẹlu lori igbimọ adajọ marun un ti Adajọ Haruna Tsammani si wọgile ipe wa loni.

    “A n jẹ ko di mimọ pe a ko tẹwọgba esi idajọ yii nitori idajọ ododo ko waye , ti inu awọn ọmọ Naijiria ko si dun si.

    “Gbọgbọ ọmọ Naijiria lo mọ pe wọn ja wa lole lọjọ kẹdọgbọn oṣu keji, ọdun 2023, ti gbogbo ajọ agbaye si bu ẹnu atẹlu ibo naa sugbọn ile ẹjọ to n gbọ awuyewuye kọ lati tẹle ohun to han si gbogbo agbaye.

    “Ipo ti ijọba awarawa wa yii, ko tẹ wa lọrun, a ko si dẹkun ninu igbinyanju lati mu ileri awọn sẹ."

  5. Oyo South: PDP, NNPP lulẹ̀, Ilé ẹjọ́ ní Alli ló borí ètò ìdìbò Sẹnẹtọ̀

    Ileẹjọ to n ẹhonu lori eto idibo sẹnẹtọ nipinlẹ Oyo wọgile ipe oludije ẹgbẹ oṣelu PDP ati NNPP lati tako esi idibo to gbe Sharafadeen Alli ti ẹgbẹ oṣelu APC wọlẹ gẹgẹ bi ẹni to bori eto idibo aṣoju ile igbimọ aṣofin agba fun guusu ipinlẹ Oyo.

    Igbimọ onidajọ gbe idajọ naa kalẹ lẹyin to wọgile ipe oludije ẹgbẹ oṣelu PDP, Oloye Joseph Tegbe lori eto idibo to waye lọjọ kẹdọgbọn oṣu keji.

    Lẹyin ti ileẹjọ wọgile ipe naa, o wa tun palasẹ fun oludije ẹgbẹ oṣelu PDP pe ko san owo toto ẹgbẹrun lọna ọọdẹgbẹta naira fun ẹnikọkan to pe lẹjọ.

    Eyi lo n jade lẹyin ti ile ẹjọ wọgile ipe ẹgbẹ oṣelu New Nigeria People’s Party ati oludije rẹ, Funmilayo Gbogbolomo, to si ni ipe ọhun ko kuna to.

    Alli ninu eto idibo naa bori ninu ẹka ile idibo toto ẹgbẹrun meji laarin ijọba ibilẹ mẹsan an to wa labẹ ẹkun idibo to wa Guusu ipinlẹ Oyo, pẹlu apapọ ibo, 111,513, ti Tegbe si ni 92,481.

  6. Ukraine war: Àdó abúgbàmù ró nínú ọjà, ṣekúpa èèyàn 16

    O kere tan eeyan mẹrindinlogun ni o ti gbẹmi mi ninu ikọlu ohun abugbamu kan to ro ni ilu Kostyantynivka ni Ukraine.

    Aarẹ Volodymyr Zelensky ẹni to da ẹbi iṣẹlẹ naa ru orilẹede Russia sọ pe “awọn ti wọn pa naa jẹ awọn eeyan ti ko ni ẹṣẹ kankan” – o si ni iye awọn to ku lee tun goke sii.

    “Aburu awọn ara Russia yii gbudọ di itẹmọlẹ lai fi akoko ṣòfò," Zelensky fi kun un.

    Awọn Aláṣẹ ni Moscow ko tii fesi si ẹsun yii.

    Ọmọde wa lara awọn mẹrindinlogun to gbẹmi mi ti o kere gan, awọn bii mejidinlọgbọn míì si fara pa.

    "Gbogbo awọn to yẹ lo n ṣiṣẹ́, Olootu ilẹ̀ Ukraine, Denys Shmyhal sọ bẹẹ o si fi kun un pe: "Wọn ti mu ọwọ ina naa wa silẹ."

    Ọjà kan awọn ile itaja ati ṣọọbu kan ti wọn ti n ta ogun lo fara kasa ohun abugbamu náà.

    Awọn fọ́nrán to jade lori ayelujara ṣafihan akoko ti o bu gbamu ati bi awọn eeyan ṣe farapa to ati bi nnkan ṣe bajẹ lẹyin iṣẹlẹ naa.

    Agbegbe kan ti ero maa n pọ si gan ni o ti ṣẹlẹ̀ gẹgẹ bi awọn eeyan ṣe n tu wọọ wọọ lọ inu awọn isọ inu ọjà ati awọn ile oúnjẹ.

    Iwadi nipa ikọlu naa to waye ti bẹ̀rẹ̀ bayii pẹlu àṣẹ olufisun àgbà ilẹ̀ Ukraine leyi ti ọfiisi rẹ ni awọn gun le ìdáwọ́lé ofin to de fífi ọwọ pa ida ofin loju.

    "Awọn agbofinro n gbe gbogbo ìgbésẹ to yẹ lati ni àkọsílẹ̀ awọn ikọlu ilẹ̀ Russia."

    Àwọn aláṣẹ Russia ko tii fẹnu sọ pe awọn làwọn ṣe ikọlu naa. Tẹ́lẹ̀ rí náà, wọ́n ti ni awọn kii ṣe ikọlu si araalu gẹgẹ bi ara gbigbogun awọn.

    Ikọlu eyi to waye l'Ọjọru ṣe kongẹ abẹwo ti akọ̀wé ìjọba ilẹ̀ Amẹrika, Antony Blinken ṣe si olú ilu Ukraine, Kyiv níbi to yẹ ko ti pade Zelensky.

  7. Iléẹjọ́ kéde Natasha Akpoti PDP gẹ́gẹ́ bíi Sẹnẹtọ tó wọlé ní Kogi, APC lulẹ̀

    leẹjọ to n gbọ ẹhonu lori eto idibo sẹnẹtọ nipinlẹ Kogi ti wogile ibo to gbe oludije ẹgbẹ oṣelu APC Sẹnẹtọ Abubakar Ohere gẹgẹ bi sẹnẹtọ aarin gbogbo ipinlẹ Kogi.

    Adajọ K,A. Orjiako kede oludije ẹgbẹ oṣelu PDP, Natasha Akpoti- Uduagan gẹgẹ bi ẹni to bori eto idibo naa.

    Lasiko to n ka idajọ naa sita, Adajọ Orjiako to lewaju igbimọ ẹlẹni mẹta ni esi to gbe Ohere wọle ni magomago ninu ni ẹka idibo mẹsan an ni ijọba ibilẹ Ajaokuta ti ajọ INEC si mọmọ din esi idibo Natasha ku ni awọn agbegbe yii.

    Bakan naa lo ni esi idibo lati ẹka idibo mẹta niu wọn mọmọ ma ka fun Natasha ni ijọba ibilẹ naa.

    Lẹyin atotonu awọn agbẹjọro, Ileẹjọ kede Natasha lati ẹgbẹ oṣelu PDP gẹgẹ bi ẹni to bori eto idibo sẹnẹtọ lẹyin to ni apapọ ibo, 54,074, ti Ohere lati ẹgbẹ oṣelu APC ni 31,291.

  8. Iléẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹ̀sùn Peter Obi lórí èsì ìbò ààrẹ

    Ile ẹjọ kotẹmilọrun nilu Abuja, ti gbe idajọ rẹ kalẹ lori ẹjọ ti oludije ẹgbẹ oselu Labour, Peter Obi pe tako esi ibo aarẹ eyi to gbe Aarẹ Bola Tinubu wọle.

  9. Ilé ẹjọ́ wọ́gilé ẹ̀sùn pé Tinubu àti Shettima kò lẹ́tọ̀ọ́ láti díje nínú ìbò ààrẹ

    Ile ẹjọ kotẹmilọrun to n ṣe idajọ lori ẹhonu to jẹyọ lori ibo aarẹ ti fagile ẹsun ti ẹgbẹ oṣelu Allied Peoples Movement pe wi pe aarẹ Bola Tinubu ati gbakeji aarẹ, Kashim Shettima ko koju oṣuwọn lati dije fun ipo rẹ.

    Ile ẹjọ naa ẹjọ ti ẹgbẹ oṣelu APM pe ko leṣẹ nilẹ.

    Igbimọ igbẹjọ naa ti awọn adajọ marun un n joko lori rẹ ni awọn ko lẹtọọ lati gbọ ẹjọ naa.

    Wọn ni ọrọ to yẹ ki wọn ti yanju ki eto idibo to waye ni.

  10. APM lulẹ̀ nílé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn tó fi tako ìyànsípò Igbákejì ààrẹ àti Tinubu, Iléẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn wọ́gilé ẹ̀sùn tẹ́gbẹ́ òṣèlú APM pè tako èsì ìbò ààrẹ, ó ní àyọnusọ ni

    Adajọ Haruna Tsammani, to ko igbimọ ẹadajọ ẹlẹni marun sodi lati ile ẹjọ kotẹmilọrun nilu Abuja, ti gbe idajọ rẹ kalẹ lori ẹjọ ti oludije ẹgbẹ oselu APM, Chichi Ojei pe tako esi ibo aarẹ eyi to gbe Aarẹ Bola Tinubu wọle.

    Ninu idajọ rẹ, adajọ naa ni olupẹjọ ko pe ẹlẹri kankan wa sile ẹjọ lati gbe awọn ẹsun rẹ lẹyin.

    Olupẹjọ yii lo n tako idibo yan Tinubu gẹgẹ bii oludije sipo aarẹ labẹ asia ẹgbẹ oselu APC, kede pe Tinubu ko yẹ lẹni to yẹ ko bonu ibo abẹnu APC lati di oludije.

    Amọ Adajọ ni ayọnisọ lasan ni olupẹjọ naa se lori ẹjọ to pe yii nitori ofin ko fi aaye gbe ọmọ ẹgbẹ oselu miran lati wa tako ibo abẹnu ẹgbẹ oselu ti kii se tirẹ.

    O fikun pe ọmọ ẹgbẹ oselu APC nikan, to si tun kopa ninu ipo abẹnu ẹgbẹ pẹlu Bola Tinubu nikan lo lẹtọ lati pe ẹjọ tako ibo abẹnu ẹgbẹ oselu naa.

    Adajọ naa ni gbogbo awọn koko ẹsun ti olupẹjọ naa gbe kalẹ lati tako ibo abẹnu ẹgbẹ oselu APC to fa Tinubu kalẹ bii ọmọ oye ni ko lẹsẹ nilẹ.

    Nigba to n gbe idajọ rẹ kalẹ lori ẹsun pe Kazzem Shettima ko yẹ lati gba ipo igbakeji Tinubu, Adajọ Tsammani wọgile ẹsun yii pe Tinubu ko lu ofin pẹlu igbakeji rẹ to yan naa.

    Adajọ naa, ẹni to wo awọn akoko ti Shettima kọ ipo oludije Sẹnetọ silẹ lati gba ipo oludije sipo igbakeji aarẹ, salaye pe ile ẹjọ Kotẹmilọrun ti gbe idajọ kalẹ saaju lori ẹjọ naa ti ẹgbẹ oselu PDP pe.

    O ni ẹjọ naa si lo gbe fun Shettimma ti ile ẹjọ to ga julọ si ni Shettima yẹ lati gba ipo igbakeji aarẹ naa.

  11. Àwọn èèkàn ẹgbẹ́ òṣèlú APC ní ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn l'Abuja

    Igbakeji aarẹ Kashim Shettima, gomina ipinlẹ Kogi, Yahaya Bello, olori awọn oṣiṣẹ ni ileeṣẹ aarẹ, Femi Gbajabiamila, gomina ipinlẹ Imo, Hope Uzodinma ree ni ile ẹjọ.

    Awọn eekan ẹgbẹ APC miiran ni minisita ileeṣẹ ọkọ ofurufu, Festus Keyamo ati oludamọran aarẹ lori ọrọ aabo, Nuhu Ribadu.

  12. Wámú wámú làwọn ẹ̀ṣọ́ alááàbò dúró níwájú ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn l'Abuja

    Wamu wamu lawọn ẹṣọ alaabo duro siwaju ile ẹjọ kotẹmilọrun to n ṣe idajọ awuyewuye lori ibo aarẹ orilẹede Naijiria to waye loṣu keji ọdun 2023 yii.

    Niṣe lawọn eṣẹ di gbogbo oju popo to lọ si ile ẹjọ naa niluu Abuja.

    Wọn o gba ẹnikẹni ti ko forukọ silẹ laye lati rin lawọn oju popo to lọ si ile ẹjọ naa..

  13. Bi Ilé ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn ṣe ń gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹ̀hónú ìbò ààrẹ rèé

    Igbimọ to n gbọ ẹhonu ibo nile ẹjọ Kotẹlọrun to wa nilu Abuja ti bẹrẹ ijoko rẹ .

  14. Ilé ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn bẹ̀rẹ̀ sí gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹ̀hónú ìbò ààrẹ tẹgbẹ oselu APM pe

    Ilé ẹjọ́ Kòtẹ́milọ́rùn bẹ̀rẹ̀ sí gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹ̀hónú ìbò ààrẹ tẹgbẹ oselu DPM pe

    Igbimọ to n gbọ ẹhonu ibo nile ẹjọ Kotẹlọrun to wa nilu Abuja ti bẹrẹ ijoko rẹ .

    Nibi ijoko naa ni yoo ti maa gbe idajọ kalẹ lori ẹsun ti Abubakar Atiku tii se oludije fẹgbẹ oselu PDP ati Peter Obi, oludije fẹgbẹ oselu Labour pe lati tako esi ibo aarẹ to kọja.

    Awọn agbẹjọro to n soju awọn olupẹjọ ati Olujẹjọ ti joko wa wa wa sile ẹjọ, ti wọn si ti safihan ara wọn.

    Bakan naa ni awọn eekan oloselu ti wa nikalẹ nile ẹjọ naa to n soju ẹgbẹ oselu kọọkan to pe ẹjọ abi eyi to n jẹjọ

    Nibayii, idajọ nipa ẹsun ti ẹgbẹ oselu APM gbe kalẹ lori ibo aarẹ nile ẹjọ naan gbe kalẹ̀ bayii.

  15. Àwọn adájọ́ ti wá ní ìjókòó fún ìdájọ́ awuyewuye lórí ìbò ààrẹ

    Awọn adajọ ati gbogbo awọn agbẹjọro lo ti wa ni ijoko nibi idajọ awuyewuye to jẹ yọ lori ibo aarẹ orilẹede Naijiria.

    Amọ, Peter Obi to jẹ oludije ẹgbẹ oṣelu Labour Party ko yọju nile ẹjọ.

    Ogbẹni Julius Abure ti pe ara rẹ ni alaga gbogbogbo ẹgbé LP lo ṣoju Obi ati ẹgbẹ naa ni ile ẹjọ.

    Igbakeji aarẹ Naijiria, Kashim Shettima atawọn gomina APC lo wa nile ẹjọ lati ṣoju Bola Tinubu ati ẹgbẹ APC.

    Abdullahi Ganduje to jẹ alaga gbogbogbo APC naa wa ni ikalẹ nile ẹjọ.

  16. Kókó, Ẹ lè wá gba káàdì ìdìbò yín láàrín ọ̀sẹ̀ mẹ́rin - INEC

    Ajọ eleto idibo ni Naijiria ti kede pe awọn yoo bẹrẹ iṣẹ fifun awọn eeyan ni kaadi idibo wọn pada fun ọsẹ mẹrin.

    Eyi n waye ṣaaju ọjọ kọkanla oṣu kọkanla, ọdun 2023 ti eto idibo gomina yoo waye ni ipinlẹ Bayelsa, Imo ati Kogi.

    Alaga ajọ eleto idibo ni laarin asiko ti wọn da yii, awọn oludibo to forukọ silẹ ti ko ri kaadi idibo wọn gba ki wọn to kede pe wọn dawọ rẹ duro ni ọjọ karun oṣu keji eyi to ṣaaju idibo gbogbogbo to kọja, wọn yoo lanfani ati gba a bayii.

    “Ajọ yii ti ya awọn ọjọ ọsẹ (Ọjọ Aje titi di ọjọ Ẹti) sọtọ lati ago mẹsan owurọ titi di ago mẹta ọsan fun gbigba kaadi idibo alalopẹ eyi ti yoo waye fun ọsẹ mẹrin laarin ọjọ kọkanla oṣu kọkanla di ọjọ kẹsan oṣu kẹwa,” Kọmisọna apapọ ajọ INEC, Sam Olumekun lo sọ eyi ninu atẹjade kan lọjọ Iṣẹgun.

    “Awọn kaadi idibo naa yoo wa nikalẹ fun gbigba ni gbogbo awọn ijọba ibilẹ to wa ni ipinlẹ mẹtẹẹta: ijọba ibilẹ mẹjọ ni Bayelsa, mẹtadinlọgbọn ni Imo ati mọkanlelogun ni Kogi.

    Lafikun, wọn ni ajọ naa ti ṣi awọn ibudo mii si awọn agbegbe ti ero pọ ti wọn ko tii gba kaadi idibo wọn ti wọn si ni ẹkunrẹrẹ nipa awn ibudo yii yoo jade latẹnu awọn kọmisọna ajọ eleto idibo ni awọn ipinlẹ mẹtẹẹta.

    Bakan naa, ajọ INEC tun pin kọmisọna ajọ eleto idibo meji si awọn ipinlẹ to ku. Kọmisọna wọn ni Edo, Obo Effanga ni yoo lọ ṣiṣẹ ni ipinlẹ Bayelsa fun idibo gomina to n bọ nigba ti Ayobami Salami yoo kuro ni ipinlẹ Ekiti lọ si Eko.

    “Awọn ipinlẹ mejeji yii wa lara awọn ti ko ni kọmisọna ajọ eleto idibo ipinlẹ latari pe saa idari awọn to di ipo naa mu kẹyin ti pari,” INEC sọ bẹẹ.

    Alaga ajọ eleto idibo Naijiria wa rọ gbogbo ẹgbẹ oṣelu atawọn oludije wọn ki wọn ṣe ohun gbogbo ni ilana alafia ki wọn si yago fun awọn ọrọ ati igbesẹ to lee da omi alafia ilu ru lasiko ipolongo idibo wọn.

  17. 'Ìfọ̀rọ̀wérọ̀ tí mo ṣe ní ọdún mẹ́fà sẹ́yìn lórí ìgbéyàwó mi ni ẹ̀ ń gbé kiri'

  18. Wọ́n ri burawọlé fún Olórí ologun adìtẹ̀gbàjọba Gabon, ó ṣèlérí ètò ìdìbò míì láìpẹ́

    Olori ijọba ologun lorilẹede Gabon ti ṣe ileri lati da agbara pada sọdọ ijọba alagbada lẹyin ti eto idibo to ba ofin mu ba waye.

    O sọ eyi lasiko to n bura wọle gẹgẹ bi Aarẹ fidihẹ ṣugbọn ko sọ ọjọ pato ti ijọba ologun yoo gbe agbara silẹ.

    Ọgagun Brice Nguema lewaju iditẹgbajọba to gba ijọba lọwọ Aarẹ tẹlẹ, Ali Bongo lẹyin eto idibo to waye kede rẹ gẹgẹ ẹni to jawe olubori.

    Ọpọ awọn eeyan lo tu sita sibi ayẹyẹ naa, ti wọn si tẹwọgba igbesẹ ologun ọhun.

    Bakan naa ni awọn mii ijọba Ọgagun Nguema ni o jẹ itẹsiwaju ọdun marundinlọgọta idile Bongo.

    Baba Ali Bongo, Omar, wa ni ijọba fun ọdun mọkanlelogoji ko to ku ni ọdun 2009, ti ọmọ si bọ si ijọba.

    Ọgagun, ẹni ọdun mejidinlaadọta lo gbogbo ogba rẹ lẹnu isẹ ologun ninu idile Bongo, ti ọpọ si ri gẹgẹ bi mọlẹbi Bongo.

    Nguema ni oun ti paa laṣẹ pe ijọba tuntun yii tu gbogbo awọn oloselu to wa ni ahamọ silẹ.

    Awọn Minisita ijọba tẹlẹ wa sibi ibura wọle naa ṣugbọn awọn araalu pariwo mọ wọn.

    Gabon ni orilẹede kẹfa to gba ominira lati ilẹ France ti ijọba ologun ti gba isakoso ijọbalaarin ọdun mẹta

  19. Iléẹjọ́ sún ìgbẹ́jọ́ Tani Olorun síwájú sí ọjọ́ kọkànlá oṣù yìí; Ohun tó ṣẹlẹ̀ rèé

  20. Àjẹbánu kò bá ti dojú Nàíjíríà bolẹ̀, èmi ni mo gba wá sílẹ̀ - Buhari