You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Ọ̀pọ̀ èèyàn di àwátì lẹ́yìn tí ọkọ̀ ojú omi ńlá kọlù afárá l’Amẹrika

Akojọpọ awọn iṣẹlẹ kaakiri agbaye

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Olumide Owaduge and Olubusola Afolayan

  1. Òjòwú ọkùnrin kan dèrò àhámọ́ Kirikiri l'Eko lórí ẹ̀sùn ìṣekúpa ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀, Lagos murder: Ọkùnrin kan kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìṣekúpa ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀

    Ọkunrin kan ti orukọ rẹ n jẹ Samuel Adeniyi ti dero ahamọ lọgba ẹwọn Kirikiri l'Eko lori ẹsun pe o fi nkan fọ ori ọrẹbinrin rẹ lagbegbe Lekki Phase 1.

    Adajọ majisreeti Patrick Nwaka ileẹjọ majisreeti to wa lagbegbe Yaba niluu Eko paṣẹ ki wọn ju Adeniyi si ahamọ lori ẹsun ipaniyan oni koko kan.

    Olupẹjọ ileeṣẹ ọlọ́pàá, Ọgbẹni Thomas Nurudeen sọ fun ileẹjọ pe ọjọ kẹwaa oṣu kẹjọ ni iṣẹlẹ yii waye ni nọmba 33, Audu Ekpa, Lekki Phase 1.

    Olupẹjọ ṣalaye pe afurasi naa ni ọrẹbinrin oun tun n fẹ ẹlọmiiran, ati pe ibalopọ ti awọn ba jọ ni papọ kìí saaba tẹ ẹ lọrun.

    A tun gbọ pe lọjọ iṣẹlẹ yii gan an, ọrẹbinrin yii to di oloogbe fi ọmọ to n tọju nibi to ti n ṣe nani silẹ, to sì lọ ba ọkunrin mii,koda irọ ni wọn ni o pa wí pe oun fẹ lọ ra kaadi si foonu ni.

    Bakan naa ni a gbọ pe Adeniyi ni lati duro de e fun ọpọ wakati ki o to o de.

    Nigba ti o pada de ni Adeniyi beere lọwọ rẹ ohun to jẹ ki o pẹ, bayii ni ọrọ naa di ìja ti Adeniyi si la hama mọ ọrẹbinrin rẹ lori.

    Olupẹjọ Nurudeen sọ fun ileẹjọ pe afurasi naa sa lọ lẹsẹkẹsẹ nigba ti wọn gbe ọrẹbinrin rẹ digba digba lọ si ile iwosan nibi ti dokita ti sọ pe ẹlẹmii ti gbaa.

    Ileẹjọ kọ lati gba ẹbẹ afurasi Adeniyi.

    Adajọ paṣẹ pe ki afurasi naa wa ni ahamọ titi ti igbẹjọ lori ẹjọ yóò fi waye ni ọjọ kẹwaa oṣu kẹwaa ọdun 2023 yii.

  2. Àwọn èèyàn fọnmú bí ààrẹ Zimbabwe ṣe yan ọmọ rẹ̀ sípò mínísítà

    Awọn ọmọ orilẹede Zimbabwe ti fi aidunnu wọn lori bi aarẹ Emmerson Mnangagwa ṣe yan ọmọkunrin rẹ sipo minisita.

    Ẹsun iṣegbe lẹyin ọmọ rẹ l'awọn ọmọ orilẹede naa fi kan aarẹ Mnangagwa. Ọjọ Aje ni aarẹ Mnangagwa kede ọmọkùnrin rẹ,

    David Kudakwashe gẹgẹ bi igbakeji minisita eto inawo. O ni eyi jẹ ara imuṣẹ ileri rẹ lati lo awọn ọdọ ninu iṣejọba rẹ.

    Bakan naa lo tun yan ọmọ ẹgbọn rẹ,Tongai Mnangagwa gẹgẹ bii igbakeji minisita irin-ajo igbafẹ gẹgẹ bi iroyin ni Zimbabwe ṣe sọ.

    Aṣoju-ṣofin to jẹ ọmọ ẹgbẹ CCC, Fadzayi Mayhere ṣapejuwe awọn minisita ti aarẹ Mnangagwa ṣẹṣẹ yan sipo gẹgẹ bii iṣegbe lẹyin awọn eeyan kan.

    Ijọba kò tíì fesi si ọrọ ti aṣofin ẹgbẹ oṣelu alatako sọ lori iyansipo awọn minisita tuntun.

    Ẹwẹ, ẹgbẹ oṣelu alatako ti sọ tẹlẹ pe eeru wa ninu eto idibo to gbe aarẹ Mnangagwa wọle loṣu to lọ

  3. Obasanjo kọrin re ki Adeleke, ó ní bó ṣe ń jó, ló ń ṣiṣẹ́ gidi lÓsun

  4. Ìdílé ẹlẹ́ni mẹ́sàn-án tí wọ́n ní ọjọ́ ìbí kan náà gba àmì ẹ̀yẹ Guinness World Record

  5. Ọmọ ọ̀dọ̀ fipá bá ọmọ ọdún márùn-ún ọmọ ọ̀gá rẹ̀ lòpọ̀, ìwádìí bẹ̀rẹ̀

  6. Ẹ̀mí 15 sọnù nínù ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi l'Adamawa

    O kere tan eeyan mẹẹdogun lo padanu ẹmi wọn nigba ti ọkọ oju omi kan danu ni ipinlẹ Adamawa lariwa Naijiria.

    Lọjọ Ẹti ni iṣẹlẹ yi waye nigba ti ọkọ oju omi naa to n gbe eeyan mẹtalelogundanu sodo.

    Ninu awọn to wa ninu kọ yi la ti ri awọn agbẹ oniṣowo ati awọn ọmọde.

    Abule Rugange lo ti gbera lọ si ilu Yola gba ori omi Njuwa.

    Iroyin to tẹwa lọwọ lati ọdọ ajọ Red Cross sọ pe wọn ti ri oku eeyan mẹrin ti igbiyanju si n tẹsiwaju lati doola awọn mii.

    Ajọ yi sọ pe atẹgun lile lo rọ lu ọkọ oju omi naa eyi to mu ko tẹri sodo pẹlu awọn eeyan to wa ninu rẹ.

    Ninu ọrọ tiẹ, akọwe ajọ to n mojuto iṣẹlẹ pajawiri ni ipinlẹ Adamawa Muhammad Amin Suleiman sọ pe eeyan meje lawọn ti ribi doolati awọn ṣi n tẹsiwaju lati ṣawari awọn meje mii.

  7. Àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì ṣẹ̀dá ọlẹ̀ ọmọ láì lo àtọ̀ àti ẹyin

  8. Àwọn agbébọn dáná sun akẹ́kọ̀ọ́ Àlùfáà ìjọ Kátólíìkì

    Awọn agbebọn kan ti dana sun ile igbe awọn Alufa ti ijọ Katoliiki, Saint Raphael to wa ni ilu Zango Kataf nipinlẹ Kaduna ti wọn si pa akẹkọọ Alufa kan.

    Eeyan kan ti iṣẹlẹ ọhun ṣoju rẹ koro sọ fun akọroyin Channels Television pe ni ọgọọrọ iye ni awọn agbebọn naa ya wọ inu “Saint Raphael Parish” to wa ni agbegbe Fadan Kamantan lalẹ Ọjọbọ ti wọn si da ina sun ile naa pẹlu ọkọ ti wọn gbe sinu ọgba ọhun.

    Iroyin tun ni oloogbe akẹkọọ Alufa naa, Stephen Danlami, ku latari eefin to n mu sinu lasiko to n gbiyanju lati sa jade ninu ile to n jona naa, nigba ti wọn ni awọn Alufa mii ninu ile ijọ naa ribi sa asala fun ẹmi wọn.

    Laipẹ lẹyin iṣẹlẹ naa, awọn alaṣẹ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ naa ni awọn gi bẹrẹ si ni wa awọn to ṣiṣẹ laabi naa.

    Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Kaduna, Manir Hassan sọ pe ọwọọwọ ni awọn agbebọn naa ya wọ ile isin naa.

    Gẹgẹ bo ṣe sọ, nigba ti awọn agbebọn naa ko ribi wọ inu ile gangan ni wọn dana sun ile naa pẹlu ọkada alupupu ati ọkọ ayọkẹlẹ to wa ninu ọgba naa.

    Agbẹnusọ ọlọpaa fi kun un pe awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju wọn sọ pe ẹni to fara kasa ku nitori eemi ti wọn mi sinu lasiko ti o n gbiyanju lati sa jade ninu ile to n jo ni.

  9. Bí Lateef tó jẹ́ Mùsùlùmí ṣe wọlé sí àwọn òbí mi lára tí wọ́n gbà kó fẹ́ mi rèé – Bimpe Adedimeji

  10. Wo àmì àrùn jẹjẹrẹ mẹ́wàá tí èèyàn le è tètè sé àkíyèsí nínú ara

  11. Ọdún Orò wáyé nílẹ̀ Benin f'ọmọ Yorùbá, wọ́n bẹ̀bẹ̀ fún àgbéga Ìṣẹ̀ṣe

  12. Ikọ̀ agbébọn ẹlẹ́sìn Islam kọlu ibùdó ológun àti ọkọ̀ ojú omi ní Mali, èèyàn 49 kú

  13. Iṣẹ́ dókítà ló wù mí àmọ́ mo di Elékuru láti ran òbí mi lọ́wọ́ – Kehinde Elekuru

  14. Ọlẹ̀ Ìbejì ń gbé bíi kòkòrò nínú ọmọ ìkókó

  15. Ọkọ àti ìyàwó ọ̀sìngín dàwátì bí omíyale ṣe gbé ilé ìgbafẹ́ lọ leti òkun

  16. Àṣìṣe ń lá ni Peter Obi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí oludije fún ẹgbẹ́ wa nínú ètò idibo Ààrẹ - Alukoro Labour Party nípinlẹ̀ Ogun

  17. Atiku ní òun kò gba ìdájọ́ Tribunal wọlé, mórilé ilé ẹjọ́ Supreme

    Oludije sipo aarẹ labẹ asia ẹgbẹ oṣelu PDP, Atiku Abubakar ni oun ko gba idajọ esi ile ẹjọ to n gbọ ẹhonu lori eto idibo aarẹ wọle, to fidi rẹ mulẹ pe Bola Tinubu lo bori eto idibo aarẹ to waye ninu oṣu keji.

    Bi ileẹjọ ṣe wọgile ipe Atiku, naa ni oun wọgile ti Peter Obi ti ẹgbẹ oṣelu LP ati ti ẹgbẹ oṣelu APM, sugbọn Atiku ni oun ti sọ fun awọn agbẹjọro oun lati ṣe oun to tọ, ki wọn si morile ile ẹjọ giga.

    “Pẹlu ibanujẹ ọkan ni mo fi n sọ fun yin pe idajọ ti ile ẹjọ gbe kalẹ yani lẹnu pupọ.

    “Mo wa n sọ fun yin pe a bọwọ fun idajọ ileẹjọ sugbọn o jẹ idajọ ti a ko tẹwọgba nitori o jina si idajọ ododo.

    “Sugbọn ijakulẹ ileẹjọ yii ko ni jẹ ki igbe ọkan mi kuro ninu igbẹkanle mi ninu ẹka ileẹjọ.

    “Bakan naa, mo ti sọ fun awọn agbẹjọro lati ma gbaradi lọ si ileẹjọ giga .

    Saaju ni ẹgbẹ oṣelu PDP na kede pe awọn tako esi ileẹjọ, ti awọn naa si kesi awọn agbẹjọro.

  18. Ìdájọ́ lásán la gbà, a kò gba ìdájọ́ òdodo èyí tó lòdì sí ìfẹ́ aráàlú - PDP/Labour

  19. Ààrẹ Ali Bongo gba òmìnira kúrò ní àhámọ́ ológun torí ìlera rẹ̀, Gabon: Àwọn ológun tó gbàjọba ní Gabon ti fún ààrẹ Bongo lómìnira torí ìlera rẹ̀ láti lọ sókè òkun

    Awọn ologun to gbajọba lorilẹede Gabon ti kede pe awọn ti tu Aarẹ Ali Bongo lominira lati lọ sibi ti o ba wu u.

    Ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ ileeṣẹ ologun, Ọgagun Ulrich Manfoumbi ka lori ẹrọ amohunmaworan, o fidi rẹ mulẹ pe awọn ologun gbe igbesẹ yii tori ilera aarẹ Bongo.

    Ọgagun Manfoumbi ṣalaye pe Bongo lanfaani bayii lati lọ soke okun itọju ara rẹ ti o ba fẹ.

    Lẹyin ti ileeṣẹ ologun gbajọba lọwọ aarẹ Bongo ni ọgbọnjọ oṣu kẹjọ to lọ, ni wọn fofin de e mọle ti ko si le jade lọ si ibi kankan.

    Igbesẹ lati fun ni ominira ko ṣẹyin ọrọ ti ajọ awọn orilẹede aarin gbungbun Afirika pe awọn ileeṣẹ ologun ni bọwọ fun Bongo gẹgẹ bi aarẹ ana ni Gabon.

    Ẹwẹ, Bongo ni arun rọpa rọsẹ lọdun 2018. Koda, ilera rẹ jẹ ohun to kọ ọpọ eeyan lominu ṣaaju eto idibo gbogbo orilẹede Gabon ọdun 2023.

  20. Akẹ́kọ̀ọ́ kú lásìkò tó ń pidán níbi ayẹyẹ ilé ẹ̀kọ́ rẹ̀