Ọ̀pọ̀ èèyàn di àwátì lẹ́yìn tí ọkọ̀ ojú omi ńlá kọlù afárá l’Amẹrika

Akojọpọ awọn iṣẹlẹ kaakiri agbaye

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Olumide Owaduge and Olubusola Afolayan

  1. Ṣé ẹ l’éèyàn ní àwọn agbègbè yìí l’Ámẹ́ríkà? Ìkìlọ ti jade fún èèyàn 170 miliọ̀nù nipa èéfín, oru

    Aworan agbegbe kan ni Amerika

    Oríṣun àwòrán, others

    O le ni eeyan miliọnu aadọsan ara Amẹrika to ti n jiyaa yala oru gbigbona tabi afẹfẹ buruku to n fẹ ti ikilọ si ti jade pe eefin buruku kan ati oru gbigbona ti di ajalu to re lu ilẹ Amẹrika. Irufẹ afẹfẹ to n fẹ lawọn apa ibi kan ti wọn n pe ni Midwest ati Mid-Atlantic ni awọn onimọ nipa ilera ti ni ko dara fun ilera awọn eniyan.

    Ẹwẹ awọn ilu bii Las Vegas ati Phoenix ti n gbaradi fun oju ọjọ gbigbona to le ni 43C (110F) ni opin ọsẹ yii.

    O kere tan eeyan bii dọsiini kan lo ti ku latari nnkan to sun mọ oru gbigbona lẹnu ọjọ diẹ bayii.

    Afẹfẹ ti ko dara to n fẹ ni wọn ti tọka okunfa rẹ si awọn nnkan to n wa latinu aginju to le ni ẹẹdẹgbẹta ni Canada bi wọn ṣe fi ọpọlọpọ eefin ranṣẹ sita bo tilẹ jẹ pe nnkan ti n dara lawọn apa ibi kọọkan ni aarin gbungbun Ila Oorun.

    Ni Ọjọ Ẹti ni wọn reti afẹfẹ ti ko dara ju ni orilẹede naa kaakiri ọpọlọpọ ilu to tan kan lati Michigan ati Ohio titi de East Coast. Afẹfẹ ti ko dara ju ni US waye ni Ọjọ Ẹti ni nnkan bii ago mẹsan wọn (14:00 BST) ni ilu New York, lẹyin naa, o tun waye ni Washington DC, ni Detroit ati Chicago gẹgẹ bi oju opo IQAir.com ṣe fi sita.

    Ajọ to n boju to aabo ayika sọ pe afẹfẹ ni awọn agbegbe yii jẹ eyi ti “ko dara fun ilera awọn eeyan kan pato” – bii awọn arugbo, ọmọ kekere atawọn to jẹ ita ni wọn ti n ṣiṣẹ tabi ka kan ṣaa ni ko dara fun ilera rara. Awọn alaṣẹ ti wa fi imọran sita jakejado ilẹ Amẹrika nipa iru afẹfẹ to n fẹ ti wọn si ni ki awọn ara New York ṣọ ilera wọn.

    Ni agbegbe Washington DC, erongba ti n waye lori iru afẹfẹ to n fẹ eyi to jẹ ki wọn wọgile ọpọlọpọ nnkan to maa n waye nita gbangba to fi mọ ikilọ kan latọdọ awọn onimọ ilera labẹle wipe ki awọn eeyan yago fun iṣẹ ti wọn n ṣe nita to ba lagbara ju ati pe ki wọn lo ibomu ti wọn ba ti wa nita.

    Ẹwẹ, ni apa Iwọ Oorun Us, ọpọlọpọ miliọnu awọn eniyan ni Nevada, Arizona ati California ni ki wọn maa reti oru gbigbona bẹrẹ lati ọjọ Abamẹta pẹlu oju ọjọ oru ti yoo goke sii si bii 43C.

    Ni Texas, ti awọn ti baba ri oju ọjọ oru to gbona to 37C fun bii ọsẹ meji bayi, o ti bẹrẹ si ni wa silẹ. Iroyin ni eeyan mọkanla lo ti ku latari ohun to sunmọ oru gbigbona ni bii agbegbe ilu Laredo lọna ibode Mexico.

    Ikilọ ti waye bakan naa fun awọn ara agbegbe East Texas bakan naa ni wọn ni iji lile ṣeeṣe ko waye ni iha Guusu eyi to yẹ ko mu oju ọjọ oru yii walẹ ni ọjọ Abamẹta ati ọjọ Aiku.

    O le ni eeyan ẹẹdẹgbẹrin to n ku latari ohun to sunmọ oru gbigbona lọdọọdun gẹgẹ bi iṣiro CDC pẹlu nnkan bii eyan ẹgbẹrun lọna mejidinlaadọrin ti wọn maa n gbe lọ si ile iwosan fun itọju pajawiri. Iji oru ti wa di lemọ lemọ bayii, o lagbara o si n pẹ gan to ba ti ja nitori awọn nnkan to jẹ afọwọfa ọmọ eniyan, awọn onimọ sayẹnsi lo sọ eyi.

    Awọ́n kan naa ti kilọ pe ayipada oju ọjọ ṣeeṣe ko mu ki ọpọ eefin pọ sii. Atẹjade kan lati Ile ẹkọ giga fasiti kan ni California – “Irvine study” eyi to jade ni ọjọ kejila oṣu kẹfa fun apẹrẹ fi iwadi han pe “oju ọjọ gbigbona yoo lọ soke sii ati ọgbẹlẹ si ti jẹ ọkan lara ohun to maa n ṣokunfa bi igbo aginju ṣe maa n jó.

  2. Iléèṣẹ́ ológun pàṣẹ fún àwọn ọ̀gá ológun kan láti fi iṣẹ́ sílẹ̀ títí ọjọ́ aje tó n bọ̀

    ọga ileeṣẹ ologun

    Oríṣun àwòrán, Twitter/ Defence H

    Ileeṣẹ ologun Naijiria ti paṣẹ fun awọn ọga ologun to ti kẹkọọ tayọ ipele kọkandinlogoji ni ile ẹkọ awọn ọmọ ologun, lati kọwe fi iṣẹ silẹ funra wọn.

    Aṣẹ naa waye lẹyin ti Aarẹ Bola Tinubu yan awọn ọga alaabo tuntun.

    Awọn ọga naa jẹ ọga fun awọn olori ileeṣẹ ologun ti aarẹ ṣẹṣẹ yàn.

    Ikede naa waye ninu atẹjade kan ti Major General Y. Yahaya fi sita ni orukọ ọga agba ileeṣẹ ologun Naijiria.

    O ni ni kiakia ni ki gbogbo awọn to ti kẹkọọ tayọ ipele kọkandinlogji kọwe fi iṣẹ silẹ.

    “Gbogbo awọn ọgagun ti ọrọ kan gbọdọ fi iwe wọn ranṣẹ si ileeṣẹ ologun, o pẹ ju, ọjọ kẹta, oṣu Keje, ọdun 2023.”

    Iru aṣẹ yii ko jẹ tuntun. Idi ni pe lara aṣa ileeṣẹ ologun ni pe awọn ọgagun kii le gba aṣẹ lọwọ ọmọ abẹ wọn to ba di ọga agba ologun.

    Nitori eyi, ko din ni ọgọrun ọgagun ti iyansipo ọga agba ileeṣẹ ologun tuntun yoo fi tipatipa mu kọwe fi iṣẹ wọn silẹ.

    Awọn General, Brigadier General, Air Vice Marshals ati Admirals ni aṣẹ naa kan nileeṣẹ ologun ori ilẹ, ori omi ati ti ofurufu.

    Ipele kejidinlogun ni olori alaabo tuntun, Major General Christopher Musa wà, nigba ti olori ileeṣẹ ologun ori ilẹ, Major General Taoreed Lagbaja, ọga agba ọmọ ogun ori aomi, Rear Admiral Emmanuel Ogalla, ati Air Vice Marshal Hassan Abubakar to jẹ ọga tuntun nileeṣẹ ologun ofurufu, wa ni ipele kọkandinlogoji.

  3. Bí àwọn olùrànlọ́wọ́ ṣe gé ẹsẹ̀ obìnrin tó há sínú ẹ̀rọ agbénifò ní pápákọ̀ òfurufú

  4. Benjamin Mendy sọ pé 10,000 obìnrin ni òun ti bá lòpọ̀ - Ẹlẹ́rìí sọ nílé ẹjọ́

  5. Ó ṣeésẹ kí owó lítà epo bẹtiró tún lọ́ sókè sí láìpẹ́ - IPMAN

    Ẹni to n ta epo sinu ọkọ̀

    Oríṣun àwòrán, Getty Images

    Ẹgbẹ awọn alagbata eporọbi, IPMAN sọ pe o ṣeeṣe ki iye ti wọn o ma a ta lita epo lọ soke kọja ẹgbẹta Naira.

    IPMAN sọ pe eyi le waye nitori ko si aridaju boya awọn oniṣowo epo yoo ri owo Dọla lati fi ra epo nilẹ okeere.

    Awọn onimọ sọ pe ni kete ti awọn alagbata epo ba fi bẹrẹ si ni ko epo wọle funra wọn laipẹ, iye ti wọn n ta lita epo yoo wọ́n si i jakejado Naijiria.

    Olori ẹgbẹ IPMAN ni Ariwa Naijiria, Bashir Dan-Mallam to fi idi iroyin yii mulẹ fun BBC Hausa, sọ pe ijọba gbọdọ gbe awọn igbesẹ to yẹ lati dena eyi.

    Dan-Mallam sọ pe ti owo Dọla ba wa nilẹ ni ọ̀pọ̀ yanturu nikan lo le dena ki owo lita epo bẹtiro ma lọ soke si i.

    Ajọ eleporọbi Naijiria, NNPC, sọ pe ida ọgbọ̀n (30%) pere ni oun yoo ma a pese ninu epo ti orilẹ-ede Naijiria nilo, ti awọn alagbata epo yoo si ma a pese eyi to kù.

    Lọwọlọwọ, N488 si N550 ni awọn ileepo n ta lita epo bẹtiro kan ni Naijiria.

  6. Allah kò ní di ẹrù tẹ́ ò ní lè gbé lée yín lórí o! Ohun táa gbọdọ̀ ṣe ní Nàìjíríà rèé – Tinubu

    Aarẹ Tinubu atawọn eekan ilu

    Oríṣun àwòrán, PRESIDENCY

    Aarẹ Bola Tinubu ti ke si awọn ọmọ Naijiria pe ki wọn nigbagbọ ninu ara wọn ki wọn si gbagbọ pe gẹgẹ bi araalu kan naa, wọn gbudọ pawọpọ lati kọ orilẹede Naijiria.

    O n sọrọ yii fun awọn oniroyin nigba to n kirun Yidi ni bareke awọn ologun Dodan Baracks. O tẹnu mọ eredi fun irẹpọ ati ifọwọsowọpọ to si n rọ awọn ọmọ Naijiria pe ki wọn pa ija ẹlẹyamẹya tabi ẹsin ti.

    “Mo dupẹ lọwọ Allah fun bi o ṣe n pa wa mọ ninu ilera pipe titi di oni mo si gbadura pe ko fun wa ni ilera ati ọrọ lọpọ yanturu. Mo gbadura ki ẹbọ wa ko yi si ilọrọ. A ni lati fi ara wa jin o si ti ye yeke yeke.

    Bakan naa, ninu ọrọ ti oluranlọwọ pataki fun aarẹ lori ọrọ iroyin Dele Alake fi sita, Aarẹ tun lo akoko naa lati gbadura fun awọn ọmọ ọmọ ogun Naijiria to wa niwaju gbigbe ogun ti sunmọmi wipe, adura ọkan oun ni wipe ki orilẹede yii pada di aṣẹgun.

    Lẹyin ti adura Yidi naa bẹrẹ ni ago mẹsan owurọ labẹ idari Imamu agba ti ipinlẹ Eko, Sheikh Sulaiman Oluwatoyin Abu-Nolah ni o pada kun ẹran agbo gẹgẹ bi ilana ẹsin Islam ati igbọran si aṣẹ Allah.

    Ki ni pataki ọdun Eid el Kabir?

    Ọgọọrọ awọn Musulumi ni inu wọn dun lati ṣe ọdun Eid al-Adha to waye ni ọjọ Kejidinlọgbọn Oṣu Kẹfa.

    Eid al-Adha ni ọdun keji ninu ọdun meji pataki ti wọn maa n ṣe ninu ẹsin Islam.

    Ọdun eleyii si yatọ si Eid al-Fitir, eyi ti wọn ṣe kẹyin ninu oṣu Kẹrin ọdun 2023.

    Ọrọ to n jẹ “Eid” tumọ si apejẹ tabi ajọdun. Ọdọọdun si nu awọn Musulumi maa n ṣe ọdun Eid al-Fitr ati Eid al-Adha.

    Ọdun Eid al-Adha yii wa tumọ si Ajọdun irubọ, wọn si maa n ṣe e lẹyin oṣu meji ti wọn ba ti ṣe Eid al-Fitr.

    Akoko ọdun maa n bọ si asiko opin Hajj – irinajo ọlọdọọdun lọ si Mecca ni Saudi Arabia, ọdun eyi si ni wọn maa n ka si mimọ ju ninu mejeji.

    Yidi

    Oríṣun àwòrán, PRESIDENCY

  7. Adeleke àti àwọn jàndùkú rẹ̀ ló kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ wàhálà ní Yídì - APC

  8. Látọ̀dọ̀ èmi Alhaja tuntun...! Wo ọ̀rọ̀ Mercy Aigbe àtàwọn gbajúmọ̀ òṣèré míì láti ilé ọdún Eid

  9. Ṣíṣe Ààrẹ Nàìjíríà ni ìpèníjà ńlá tí mo kojú jùlọ nílé ayé - Buhari

    Muhammadu Buhari

    Oríṣun àwòrán, Muhammadu Buhari

    Ààrẹ àná ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, Muhammadu Buhari ti júwe ṣíṣí Ààrẹ Nàìjíríà gẹ́gẹ́ bí ìpèníjà ńlá nínú ìgbésí ayé òun.

    Buhari sọ èyí nínú ọ̀rọ̀ ìkíni kú ọdún tó fi ránṣẹ́ sí àwọn Nàìjíríà.

    Àtẹ̀jáde kan tí Mallam Garba Shehu fi síta lórúkọ Buhari rọ àwọn ọmọ Nàìjíríà láti gbárùkù ti Tinubu kó lè ṣe àṣeyọrí

    Ó ní ṣíṣe olórí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà jẹ́ ohun tó le díẹ̀ àti pé jíjẹ́ olórí gba kí ènìyàn ní ìfarajìn kó sì rí àtìlẹyìn àwọn ènìyàn rẹ̀.

    Lẹ́yìn náà ló kí àwọn Mùsùlùmí kú ayẹyẹ ọdún Iléyá, tó sì tún gbà á ní àdúrà pé ayọ̀ ni àwọn tó wà ní Mecca máa fi darí wálé.

    Àwọn ọ̀rọ̀ yìí ló ń wáyé lẹ́yìn tí Buhari fi ohùn kan léde pé ká ní òun yọ ìrànwọ́ orí epo bẹntiróòlù, ó ṣeéṣe kí Tinubu ma wọlé ìbò Ààrẹ.

    Ẹ ó rántí pé ní ọjọ́ Kọkàndínlọ́gbọ̀n ni Buhari gbé ìjọba Nàìjíríà kalẹ̀ fún Ààrẹ Tinubu ti ìlú dìbò yàn nínú ètò ìdìbò ọjọ́ Kẹẹ̀dọ́gbọ̀n, oṣù kejì ọdún 2023.

  10. Mo mọ ìnira tí ẹ̀ ń kojú lórí àìrajaja ọrọ̀ ajé - Tinubu

    Asiwaju Bola Ahmed Tinubu

    Oríṣun àwòrán, Asiwaju Bola Ahmed Tinubu

    Ààrẹ Nàìjíríà, Bola Tinubu ti rọ àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè yìí pàápàá àwọn Mùsùlùmí láti ní ẹ̀mí ìgbàmọ́ra àti sùúrù gẹ́gẹ́ bí Ànọ́bì Ibrahim bí ọdún Iléyá ṣe wọlé dé wẹ́rẹ́.

    Bákan náà ló rọ àwọn tórí bẹ́gi ọlà fún láti máa rántí àwọn aláìní.

    Tinubu sọ èyí lẹ́yìn tó padà sí Nàìjíríà lẹ́yìn ìrìnàjò rẹ̀ lọ sí orílẹ̀ èdè France.

    Ààrẹ Tinubu ní àkókò láti lékún nínú ṣíṣe ìtọrẹ àánú fún àwọn tí kò rí jájẹ tó ni àsìkò yìí àti pé àwọn ènìyàn nílò láti túnbọ̀ máa tẹra mọ́ iṣẹ́ rere.

    "A dúpẹ́ fún Ọlọ́run tó jẹ́ kí ayẹyẹ ọdún Iléyá mìíràn tún ṣojú wá."

    Nígbà tó ń júwe ọdún Iléyá gẹ́gẹ́ bí àsìkò tí ènìyàn máa ń juwọ́ àti ẹsẹ̀ kalẹ̀ fún Allah ní ó yẹ kí ìṣe Ànọ́bì Ibrahim máa wà nínú gbogbo ọmọ Mùsùlùmí ni.

    Ó fi kun pé ìṣèjọba tó wà lóde lábẹ́ ìdarí òun ń gbìyànjú láti mú ayé rọrùn fún gbogbo ènìyàn.

    Ó tẹ̀síwájú pé òun mọ ìpèníjà tí àwọn ènìyàn ń kojú nípa ètò ọrọ̀ ajé tí kò ra jaja tó, àti pé gbogbo ìgbésẹ̀ ni àwọn n gbé láti kojú àwọn ìṣòro náà.

    Tinubu parí ọ̀rọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú kíkí àwọn ọmọ Nàìjíríà kú ọdún, pé ọdún a yabo fún gbogbo wa.

  11. Ẹ wo bí ẹbí àti ẹni tí wọ́n fẹ́ lọ yọ kíndìnrín rẹ̀ lókè òkun ṣe ń gbé nínú ìbẹ̀rù

  12. Iléèṣẹ́ ọlọ́pàá Naijiria kó ọlọ́pàá kúrò lọ́dọ́ àwọn èèyàn pàtàkì nílùú

    Awọn ọlọpaa to duro

    Oríṣun àwòrán, AFP

    Àwọn alaṣẹ ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria ti kede erongba rẹ lati ko awọn ọlọpaa to n ṣọ́, tabi to n tẹle awọn eeyan pataki kuro lọdọ wọn.

    Adele ọga agba ọlọpaa, Olukayode Egbetokun sọ pe awọn yoo ko awọn ọlọpaa naa kuro, lati pin wọn si iṣẹ aabo ilu.

    O ni lootọ ni aabo awọn eeyan pataki niluu ṣe koko, “ṣugbọn o ṣe pataki ka mojuto awọn nnkan to yẹ lati yanju iṣoro to n koje eto aabo ni Naijiria”.

    Egbetokun sọ, gẹgẹ bi akọsilẹ iwe iroyin Premium Times pe awọn ibi to ṣe koko nikan ni wọn o da ọlọpaa pada si fun awọn eeyan pataki.

    Aipẹ yii ni Egbetokun gba iṣẹ adele ọga agba ọlọpaa lẹyin ti Aarẹ Bola tinubu da awọn ọga ajọ alaabo gbogbo duro.

  13. Irọ́ ní ìròyìn pé a fowó kún owó iná - AEDC

  14. Wo àwọn ìgbésẹ̀ kọ̀ọ̀kan nínú iṣẹ́ Hajj

  15. Nítorí kí APC le jáwé olúborí ìbò ni Buhari kò ṣe yọ 'subsidy' - Garba Shehu

    Tinubu, Garba Shehu ati Buhari

    Oríṣun àwòrán, COLLAGE

    Agbẹnusọ Ààrẹ àná Nàìjíríà, Garba Shehu ti ṣàlàyé ìdí tí Muhammadu Buhari kò ṣe yọ ìrànwọ́ orí epo bẹntiróòlù nígbà tó wà nípò.

    Garba Shehu ní Buhari kọ̀ láti yọ ìrànwọ́ orí epo nítorí pé kò ì tíì tó àkókò tó yẹ kí wọ́n gbé ìgbésẹ̀ bẹ́ẹ̀ kí wọ́n tó kúrò lórí ipò.

    Nínú àtẹ̀jáde kan tí Shehu fi síta lọ́jọ́ Ajé ní ìjọba Muhammadu Buhari mọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe ìdádúró yíyọ ìrànwọ́ orí epo náà fún àsìkò tó yẹ ni.

    Ó ní irú ìgbésẹ̀ kò lè wáyé lásìkò tí gbogbo nǹkan ń gbóná ní Nàìjíríà àti pé olórí rere kò ní hu irú ìwà bẹ́ẹ̀.

    Agbẹnusọ Ààrẹ àná náà ní ìjọba tuntun tó mọ nǹkan tó ń ṣe, tó sì ní ẹ̀mí láti ṣe dada fún àwọn ará ìlú nìkan ló le gbé ìgbésẹ̀ tí Tinubu gbé.

    Ó fi kun pé lára ìdí tí Buhari kò fi yọ ìrànwọ́ orí epo lásìkò tó ti fẹ́ gbé ijoba sílẹ̀ ni láti ri pé ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC) jáwé olúborí ìbò Ààrẹ.

    Ó ní àwọn ọmọ Nàìjíríà kò ní dìbò fún APC tó bá jẹ́ wí pé Buhari ti yọ ìrànwọ́ orí epo náà bí ètò ìdìbò ṣe ń bọ̀ lọ́nà.

    "Nígbà tí a ti dìbò tán, olórí tó bá mọ ohun tó ń ṣe gbọ́dọ̀ wá ọ̀nà láti tẹ̀síwájú."

    "Mo ní ìgboyà nínú ìjọba tuntun yìí pé wọ́n máa ṣe àgbékalẹ̀ àwọn ètò lọ́kan-ò-jọ̀kan tó máa mú àyípadà rere bá ètò ọrọ̀ ajé Nàìjíríà."

    Bákan náà ló gbóríyìn fún Ààrẹ Tinubu àti igbákejì rẹ̀, Kashim Shettima fún yíyọ ìrànwọ́ orí epo àti ríri pé owó dọ́là jẹ́ bákan náà lọ́jà.

    Shehu tún kan sáárá sí wọn pé wọ́n ṣe ètò náà dáadáa débi wí pé kò sí wàhálà kankan tó wáyé lẹ́yìn àwọn ìgbésẹ̀ yìí.

    Ó tẹ̀síwájú pé bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀gá òun kò yọ ìrànwọ́ orí epo bẹntiróòlù, ó ní ọ̀pọ̀ ìrànwọ́ ni Buhari yọ bíi ti orí kẹrosíìnì, iná mọ̀nàmọ́ná àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.

    Ó fi kun pé ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé ọ̀pọ̀ àwọn ìrànwọ́ tí Buhari yọ yìí ló ti máa ń ṣe àkóbá fún ètò ìsúná Nàìjíríà.

  16. Ààrẹ Tinubu yí orúkọ àwọn Pápákọ̀ Òfurufú padà; Orúkọ wọn tuntun rèé

    Aarẹ Bola Tinubu

    Oríṣun àwòrán, OTHERS

    Ijọba Aarẹ Bola Tinubu ti fun awọn papakọ ofurufu ti ijọba kọọkan ni orukọ miran to si fi wọn sọ orukọ awọn eeyan jankanjankan ni Naijria.

    Eyi jẹ jade ninu iwe atẹjade kan to wa latọdọ ileeṣẹ to n ri si irina ofurufu eyi ti Oludari ẹkan kan ni ileeṣẹ naa, Arabinrin Joke Olatunji buwọlu ni ọjọ Kinni Oṣu Kẹfa Ọdun 2023.

    Atẹjade naa jẹ ko di mimọ pe igbesẹ aarẹ jẹ ọkan lara awọn atunṣe to n waye lẹka irina ofurufu.

    Ààrẹ Tinubu fi orúkọ Ààrẹ ana, Muhammadu Buhari sọ Papakọ ofurufu ti ilu Maiduguri nigba ti ti Port Harcourt gba orúkọ Oloogbe Akinkanju nni, Obafemi Awolowo. Bẹẹ si ni Papako Ofurufu ti Ìpínlẹ̀ Nasarawa ti n jẹ orúkọ oludasilẹ ìlú Sokoto, Usman Dan Fodio.

    Bakan naa, wọn yi orúkọ Papako Ofurufu Benin pada si orúkọ Ọba Benin tẹlẹ̀, Oloogbe Ọba Akenzua ll. Papako Òfurufú Ebonyi ti n jẹ orúkọ Ààrẹ ile aṣofin tẹ́lẹ̀ rí, Chuba Okadigbo nigba ti ti ilu Ibadan ti gba orúkọ adari ẹkùn Ìwọ Oòrùn àtijọ́ (Western Region), Oloogbe Ladoke Akintola.

    Ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ àwọn Papako Ofurufu to gba orúkọ tuntun rèé:

    1. Akure Airport – Olumuyiwa Bernard Aliu

    2. Benin Airport – Oba Akenzua II

    3. Dutse Airport – Muhammad Nuhu Sanusi

    4. Ebonyi Airport – Chuba Wilberforce Okadigbo

    5. Gombe Airport – Brigadier Zakari Maimalari

    6. Ibadan Airport – Samuel Ladoke Akintola

    7. Ilorin Airport – Gen. Tunde Idiagbon

    8. Kaduna Airport – Hassan Usman Katsina

    9. Maiduguri Airport – Gen. Mumammadu Buhari

    10. Makurdi Airport – Joseph Sarwuan Tarka

    11. Minna Airpor – Mallam Abubakar Imam

    12. Nassarawa Airport – Sheikh Usman Dan Fodio

    13. Osubi Airport – Alfred Diete Spiff

    14. Port Harcourt Airport – Obafemi Jeremiah Awolowo

    15. Yola Airport – Lamido Aliyu Mustapha

  17. Èèyàn mẹ́rin fi ara pa níbí gáàsì tó gbiná ní Eko

    Eeyan mẹrin lo farapa lasiko ti afẹfẹ idana gaasi gbina ni agbegbe Agege nipinlẹ Eko.

    Ajọ to n mojuto iṣẹlẹ pajawiri nipinlẹ naa, LASEMA, sọ ninu atẹjade pe owurọ ọjọ Aje ni gaasi naa gbina ni ile itaja kan to wa ni ẹgbẹ ile ijọsin The Apostolic to wa ni Agege.

    Agbẹnusọ ajọ LASEMA, sọ pe iwadii fihan pe ọ̀kan lara awọn agolo gaasi ti wọn n ta ni ile ṣọọbu naa lo deede bu gbamu, ti ina si sọ.

    Ṣọọbu ti wọn ti n ta gaasi nikan lo jona, nitori awọn oṣiṣẹ panapana ati adoola tete pa ina naa.

    LASEMA sọ pe eeyan mẹrin, obinrin mẹta ati ọkunrin kan lo farapa nibi ibugbamu naa, ti awọn oṣiṣẹ adoola si ti ko wọn lọ si ileewosan ikọṣẹ iṣegun fasiti ipinlẹ Eko, LASUTH.

    Awọn to farapa

    Oríṣun àwòrán, Lasema

  18. Obìnrin tó wọ ọkọ̀ 'Uber' yìnbọn lu dẹrẹbà tórí ó rò pé àjínigbé ni

  19. Ìséde bẹ̀rẹ̀ lẹyìn tí agbébọn pa èèyàn 20 níbi ayẹyẹ ọjọ́ ìbí

    Aworan awọn agbofinro

    Oríṣun àwòrán, AFP

    Aarẹ orileede Honduras ti kede konileogbele ni ilu kan ti awọn eeyan mẹtala padanu ẹmi wọn ninu iṣẹlẹ iyinbọnpaniyan lọjọ Abamẹta.

    Aarẹ Xiomara Castro ṣapejuwe iṣẹlẹ yi to waye ni Choloma gẹgẹ bi eleyi ti o jẹ ikọlu agbesunmọmi to buru julọ .

    Awọn to padanu ẹmi wọn nibi apejẹ ayẹyẹ ọjọ ibi yi jẹ ọkunrinn mejila ati obirin kan.

    Iṣẹlẹ ipaniyan miran to waye ni agbegbe Sula Valley bakan naa mu ki iye eeyan to padanu ẹmi wọn jẹ nkan bi eeyan ogun.

    Awọn alaṣẹ ni iṣẹlẹ wọnyi ni ṣe pẹlu awọn ikọ janduku to n ta oogun oloro.

    Iṣede ti aarẹ kede yi yoo bẹrẹ ni ago mẹsan alẹ titi di ago mẹrin owurọ kutu ọjọ Aiku ti yoo si tẹsiwaju bẹẹ o kere ju laarin ọjọ mẹẹdogun.

    Yoo tẹsiwaju de ilu San Pedro Sula to jẹ ilu to tobi ṣikeji ni orileede naa.

    Ọjọ Kẹrin oṣu Kejila ni yoo bẹrẹ nibẹ.

    Arabinrin Castro sọ pe awọn ti n ṣeto lati koju awọn janduku ọdaran ikọ oloogun oloro ti awọn baba isalẹ n ṣatilẹyin fun.

    O ni ''aimọye ikọlu laa n ṣeto si awọn janduku yi ti a si tun ṣeto ibudo ayẹwo''

    Ijọba orileede Honduras fikun pe awọn yoo fi agbofinro ẹgbẹrun kan ranṣẹ lafikun si agbegbe naa.

    Bẹẹ ni wọn kede owo ẹbun ẹ́gbẹrun mẹtalelọgbọn dọla fẹnikẹni to ba le ta agbofinro lolobo awọn to wa nidi iṣẹlẹ yi iyinbọnpaniyan Choloma yii.

  20. Èèyàn márùn ùn kò àgbákò ikú lọ̀wọ̀ agbébọn ní Kenya

    O kere tan eeyan marun un lo ku ti awọn afurasi agbebọn ikọ alakatakiti Al Shabab si danọ sun aimọye ile ni abule kan ni agbegbe Lamu lorileede Kenya.

    Ileeṣẹ ọlọpaa jabọ pe awọn agbebọn yi ti wọn to ogun si ọgbọn ṣe ikọlu si abule naa lalẹ ọjọ Abamẹta ti wọn si fi ọbẹ du awọn eeyan ti ọwọ wọn tẹ nibẹ.

    Arakunrin to moribọ ṣalaye fun awọn ọlọpaa pe niṣe lawọn agbebọn yi wọ aṣọ to farajọ ti awọn ọmọ ileeṣẹ ologun.

    Ikọlu yi waye lẹyin ọṣẹ kan ti ọkọ awọn ọmọ ogun tẹ ado oloro kan ti wọn ri mọlẹ laarin oju ọna.

    Awọn ọmọ ogun meji ku ti aimọye si farapa ninu isẹlẹ naa.

    Agbegbe Lamu to jẹ ibi kan to wa lẹba aala ibode Kenya ati Somalia a maa koju ikọlu lemọlemọ lọwọ awọn ọmọ ikọ Al-Shabab.

    Ọ́dun mẹsan sẹyin ni ẹmi eeyan ọọdunrun ṣofo ninu ikọlu ti wọn ṣe si ilu Mpeketoni lagbegbe Lamu.

    Lati nkan bi ọdun mejila sẹyin si ni wọn ti sọ agadagodo si aala ibode orileede mejeeji yi.

    Amọ laipẹ yi ni Minisita feto aabo labẹlẹ Kenya kede pe wọn yoo ṣi ibode to kọja ni Lamu,Garissa ati Mandera laarin ọọdunrun ọjọ.

    Aworan awọn agbegbọn ikọ al Shabab

    Oríṣun àwòrán, AFP