Ìgbìmọ̀ tó ń gbọ́ ẹ̀hónú ìbò ìpínlẹ̀ Eko ti ní ọjọ́ kan náà
ni òhun yóò gbé ìdájọ́ kalẹ̀ lórí ẹjọ́ tí gómìnà ìpínlẹ̀ náà, Babajide Sanwoolu
àti igbákejì rẹ̀, Obafemi Hamzat pè.
Bákan náà ni wọ́n ní ọjọ́ tí àwọn máa gbé ìdájọ́ kalẹ̀ yìí
náà ni àwọn máa dájọ́ lórí ẹjọ́ tí àjọ elétò ìdìbò ilẹ̀ wa INEC pè.
Níbi ìjókòó ìgbẹ́jọ́ náà tó wáyé lọ́jọ́ Àbámẹ́ta, ọjọ́ kẹta
oṣù Kẹfà ọdún 2023, ìgbìmọ̀ ẹlẹ́ni mẹ́ta ọ̀hún tí Adájọ́ Arum Ashom ṣáájú rẹ̀
ní ọjọ́ kan ni àwọn máa gbé gbogbo ìdájọ́ kalẹ̀.
Gómìnà ìpínlẹ̀ Eko, Babajide Sanwoolu àti igbákejì rẹ̀,
Obafemi Hamzat ló pẹjọ́ pé kí ìgbìmọ̀ náà da ẹjọ́ tí olùdíje sípò gómìnà Eko lẹ́gbẹ́
òṣèlú Labour Party, Gbadebo Rhodes-Vivour ti kọ́kọ́ gbé síwájú wọn nù.
Agbejọ́rò gómìnà Eko àti igbákejì rẹ̀, Wole Olanipekun níbi
ìgbẹ́jọ́ níẹjọ́ tí Rhodes-Vivour pè
láti tako ìjáwé olúborí Sanwoolu níbi ètò ìdìbò tó wáyé lọ́jọ́ kejìdínlógún oṣù
Kẹta kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ àti pé kò ṣàlàyé ìdí tó fi lẹ́tọ̀ọ́ láti pe àwọn lẹ́jọ́.
Olanipekun fi kun pé Rhodes-Vivour nìkan ló dá pe ẹjọ́ tí ẹgbẹ́
òṣèlú tó díje lábẹ́ rẹ̀ kò sí nínú àwọn tó ń pè ẹjọ́ láti tako bí Sanwoolu ṣe
gbégbá orókè níbi ètò ìdìbò náà.
Ó ní ìgbésẹ̀ yìí tako òfin ètò ìdìbò ọdún 2022 tó sì rọ ilé ẹjọ́
láti da ẹjọ́ náà nù pátápátá.
Nígbà tó ń fèsì, Rhodes-Vivour gba tẹnu agbejọ́rò rẹ̀,
Olumide Ayeni ní òfin ètò ìdìbò ọdún 2022 náà ti fi ààyè gba olùdíje láti pé ẹjọ́
fúnra rẹ̀ láìsí àtìlẹyìn ẹgbẹ́ to bá gbe dìde.
Rhodes-Vivour fi kun pé ẹjọ́ tí òun pè kò ní ẹja n bákàn
nínú àti pé kí ilé ẹjọ́ má gba ẹjọ́ tí gómìnà àti igbákejì rẹ̀ pè láàyè.
Lẹ́yìn gbogbo atótónu àwọn agbejọ́rò méjéèjì ni ìgbìmọ̀ ọ̀hún
rọ̀ wọ́n láti ri pé wọ́n gbé àwọn ẹ̀rí wọn síwájú ìgbìmọ̀ kó tó di ọjọ́ Kẹrìndínlógún
oṣù Kẹfà.
Adájọ́ Ashom tún sún ìgbẹ́jọ́ síwájú di ọjọ́ Ajé, ọjọ́
Karùn-ún tí ìgbẹ́jọ́ yóò tún tẹ̀síwájú.