Ìjìyà tí àjọ ECOWAS n fún Niger tí bẹ̀rẹ̀ sí fa ọ̀wọ́n gógó owó ọjà
Ìjìyà tí àjọ ECOWAS n fún Niger tí bẹ̀rẹ̀ sí fa ọ̀wọ́n gógó owó ọjà
Awọn olùgbé ni àwọn agbegbe kan ni orile-ede Niger ti bẹrẹ si ké ìrora nitori owó gege to gun ori ọjà lẹyin ti ìjọba ológun ti ẹnubodè.
Diẹ lara awọn ọmọ orile-ede naa, paapa awọn oniṣowo, lo ti fi owo kún owó ọjà, pẹlu awawi pe igbesẹ wọn ko ṣẹyin awọn ijiya tó bá orile-ede naa nitori iditẹgbajọba to waye ni Ọjọ́rú ọ̀sẹ̀ to kọja.
Eyi n waye lasiko ti awọn orile-ede to wa ninu àjọ ECOWAS (akojọpọ àwọn orile-ede to n ṣe ọrọ̀ ajé pọ̀ ni Ìwọ-oòrùn Africa) ti ti n fi opin si karakata pẹlu Niger.
Orile-ede Benin to pààlà pẹlu Niger ni Ariwa, ti ti ibodè rẹ pa.
Yatọ si ijiya yii, Ecowas tun fun awọn ológun naa labẹ ìṣàkóso Ọgagun Abdourahmane Tchiani ni gbedeke ọ̀sẹ̀ kan lati da Basoum pada sipo
Bakan naa ni awọn ológun to gba ijọba lọwọ Aarẹ Mohamed Bazoum, kede pe àwọn ti ti ibode orile-ede naa lori òkun, ofurufu, ati ori ilẹ̀.
Akọroyin BBC Hausa, Tchima Ila Issoufou, jábọ̀ pé owó ọjà rírà ti wọn gan-an niluu Yamai, olu ilu orile-ede Niger.