Ìjọba ológun ní Niger yan olóòtú ìjọba tuntun fún orílẹ̀-èdè nàá
Olori ijọba ologun to ditẹgbajọba ni Niger, Ọgagun Abdourahmane Tchiani , ti kede ẹni to ti fi igba kan jẹ minisita fun eto ẹnawo gẹgẹ bi olootu ijọba.
Ali Mahaman Lamine Zeine n rọpo Mahamadou Ouhoumoudou, to wa nipo naa tẹlẹ. Ilẹ europe lo wa nigba ti iditẹgbajọba naa waye lọjọ kẹrindinlọgbọn, oṣu Keje.
Ọgbẹni Zeine to ti le ni aadọta ọdun, jẹ minisita eto ẹnawo lati ọdun 2001 titi di igba ti awọn ologun gba ijọba lọwọ Aarẹ Mamadou Tandja to ti di oloogbe bayii lọdun 2010.
Agbẹnusọ ijọba ologun kan lo kede iyansipo rẹ ninu atẹjade kan lori amohunmaworan ijọba orilẹ-ede naa, Téle Sahel, ni alẹ ọjọ Aje.
Ṣaaju asiko yii, Ọgbẹni Zeine ti ṣiṣẹ ni African Development Bank ni Chad, Ivory coast ati Gabon, gẹgẹ bi akọsilẹ nipa rẹ loju opo ayelujara ActuNiger.
Yatọ si iyansipo Zeine, ijọba ologun naa tun yan Brig.Gen Amadou Didili gẹgẹ bi olori ajọ High Authority for Peace Consolidation (HACP) ati Brig Gen Abou Tague Mahamadou gẹgẹ bi ọga agba ileeṣẹ ologun.
O tun yan Col Ibro Amadou Bachirou gẹgẹ bi olori awọn oṣiṣẹ fun olori ijọba ologun naa, ati Lt Col Habibou Assoumane gẹgẹ bi olori awọn ẹṣọ alaabo fun aarẹ ologun.