Ọ̀pọ̀ èèyàn di àwátì lẹ́yìn tí ọkọ̀ ojú omi ńlá kọlù afárá l’Amẹrika

Akojọpọ awọn iṣẹlẹ kaakiri agbaye

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Olumide Owaduge and Olubusola Afolayan

  1. Gbogbo akẹ́kọ̀ọ́ Nàìjíríà tí ogun lé ní Sudan láti dá padà sílé-NIDCOM

    Isi ikẹẹdogun awọn akẹkọọ ọmọ Naijiria ti ogun le kuro ni Sudan ti pada sile.

    Pẹlu igbesẹ yi,gbogbo awọn akẹkọọ Naijiria ti wọn gbe lati papakọ ofurufu Egypt pada sile ni wọn ti ko tan bayii.

    Bẹẹ ni Abike Dabiri Erewa to jẹ ọga agba ajọ Naijiria to n risi ọrọ ọmọ ilẹ Naijiria nilẹ okere ti ṣe kede loju opo Twitter rẹ.

    Dabiri sọ pe awọn akẹkọọ 147 to gbera lati papakọ ofurufu Port Sudan balẹ si papakọ ofurufu Nnamdi Azikwe,Abuja, ni nkan bi ago mẹjọ abọ alẹ ọjọ Abamẹta.

    ''Ni paapa gbogbo awọn akẹkọọ wa lo ti dari pada sile bayii''

    Lapapọ ajọ naa sọ pe awọn ti ribi gbe awọn ọmọ Naijiria 2,518 pada sile.

    Bẹẹ ni wọn fi kun pe ko si ẹmi eeyan kankan to padanu lasiko ti wọn n gbe wọn pada sile.

    A ko le fidi rẹ mulẹ wi pe gbogbo ọmọ Naijiria ti ogun le ni Sudan lo pada sile bayii nitori ọpọ ni ko gba ọna ti Egypt sa asala tori ogun Sudan.

    Skip X post
    Allow X content?

    This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

    Warning: The BBC is not responsible for the content of external sites.

    End of X post

  2. Ukraine-Russia War: Ààrẹ ilẹ̀ Ukraine sèpàdé pẹ̀lú Pope Francis ní Rome

    Aworan

    Oríṣun àwòrán, Reuters

    Adari ijọ Aguda lagbaye, Pope Francis ti sọ fun aarẹ orilẹede Ukraine, Volodymyr Zelensky pe oun yoo ma gbadura fun alaafia ni gbogbo igba.

    Pope Francis sọ eyi lasiko ti oun se ipade pọ pẹlu Zelensky ni Vatican, ni Rome.

    Adari naa ni awọn eniyan nilo iranwọ lasiko ogun naa to ti bẹrẹ lati ọdun kan sẹyin.

    Saaju ni Zelensky ti sepade pọ pẹlu Olotu ijọba ilẹ Italy, Giorgia Meloni, pẹlu ileri pe awọn yoo tẹsiwaju lati maa se atilẹyin fun Ukraine ninu ogun to n lọ lọwọ naa.

    O kere tan naa, ikọ ọmọogun to le ni ẹgbẹrun kan lo wa ni sẹpẹ fun ipade naa, ti wọn ko si gba ki ọkọ ofurufu kankan kọja lasiko yii.

    Ninu atẹjade ti wọn fi lede ni wọn ti ni ọrọ oselu ati ọrọ ipenija ounjẹ ati iranwọ fun awọn ara ilẹ Ukraine ni aarẹ ilẹ naa jiroro pẹlu Pope Francis.

    Wọn fikun un pe ogoji isẹju ni wọn fi se ipade naa laaarin ara wọn.

    Aarẹ Zelensky ati Pope Francis jọ jumọ sọ wi pe, eto iranwọ gbọdọ tẹsiwaju fun awọn araalu lasiko yii, titi ti ogun naa yoo fi ka kuro nilẹ.

  3. Fídíò sàfihàn bí Seun Kuti se fọ́ ọlọ́pàá létí, ọ̀gá ọlọ́pàá pàṣẹ́ kí wọn fi pańpẹ́ mu

    Aworan

    Oríṣun àwòrán, Getty Images

    Orukọ gbajugbaja olorin Afrobeat, Seun Kuti lo gba ori ẹrọ ayelujara kan lẹyin ti fidio ṣafihan bi o sẹ fi iya jẹ ọlọpaa kan.

    Ninu fidio to n ja ranyin lori ẹrọ ayelujara naa ni Kuti ti fọ ọlọpaa to wọ aṣọ iṣẹ naa leti.

    Lẹyin to fọ leti tan lo tun bẹrẹ si ni sọ ọrọ kubakugbe si.

    Amọ ko si ẹni to lee fi idi ohun to ṣẹlẹ ninu fidio naa mulẹ, to fi mu ki Kuti kọju ija si ọlọpaa naa.

    Amọ ninu fidio naa, ọlọpaa naa ko fọhun, ti ko si fun Seun Kuti ni esi ihuwasi naa.

    Ninu fidio naa ni Kuti ti n bere wi pe se ọp̣ọlọ ọlọpaa naa pe bayii?

    Ọga ọlọpaa paṣẹ ki wọn fi panpẹ ọba mu Seun Kuti – Ọga Agba Ọlọpaa

    Ọga agba ọlọpaa lorilẹede Naijiria, IGP Usman Alkali Baba ti paṣẹ fun kọmisọnna ọlọpaa lati fi panpẹ ọba mu Seun Kuti.

    Eyi ko sẹyin fidio to safihan bi Kuti se fọ ọlọpaa leti, to si tun sọrọ kubakugbe si.

    Bakan naa lo si tun paṣ̣ẹ iwadii ni kiakia lori isẹlẹ naa, ki wọn si tun fi ọwọ ofin mu Seun Kuti ọhun.

    O wa fi da awọn araalu loju pe awọn ko ni fi aye gba ki ẹnikẹni maa hu iwa aitọ si awọn ọlọpaa ni awujọ.

    Ọlọpaa naa fẹ pa emi ati ẹbi mi ni,o si ti bẹbẹ- Seun Kuti

    Amọ ninu atẹjade ti Seun Kuti fi si ori Instagram, o ni nise ni ọlọpaa naa fẹ gba ẹmi oun ati awọn mọlẹbi oun, ni oun se gbe igbesẹ naa.

    Bakan naa lo ni ọlọpaa naa ti tọrọ idariji ni ọwọ oun, fun ohun to se.

    ‘’O fẹ pa emi ati awọn mọlẹbi mi, ti mo si ni ẹri to daju, amọ mi o ki n lepa eniyan lai ni idi.''

    ''Ọlọpaa naa ti bẹbẹ, mo si ti dariji pe mi o ni fi ẹsun kan an, ẹyin ti ọrọ ko kan, ẹ gbe ẹnu yin dakẹ, ẹ ma jẹ ki ọkunrin yii padanu iṣẹ rẹ.''

  4. Gbajúmọ̀ òṣèré tíátà, Mukaila Adedigba ti jáde láyé

  5. Ẹ̀yin tẹ́ẹ fẹ́ máa ṣe "prank" pa owó bíi tèmí, ẹ má dán an wòo torí adúrú ìyà tó ń jẹ mi yìí - Trinity guy

  6. Ọkọ fẹ ìyàwó rẹ̀ padà lẹyìn tó lẹ̀dí àpò pọ̀ jí ọmọ rẹ̀ gbé gba owó N3m

    Lọpọ ibi ni ilu Kano,niṣe lawọn eeyan ṣi n tẹnumọ iroyin iṣẹlẹ to waye ni olu ileeṣẹ ọlọpaa lỌjọbọ ọjọ Kọkanla oṣu Kaarun.

    Lọjọ taa n wi yi, awọn ọlọpaa ṣafihan ọpọ awọn afurasi lori ẹsun orisirisi.

    Ninu wọn ni arabinrin ẹni ọdun marundinlọgbọn kan wa to ji ọmọ bibi inu rẹ obinrin Hafsa Kabiru.

    Gẹgẹ bi alukoro ọlọpaa Abdullahi Haruna Kiyawa ṣe sọ, obinrin naa ati ọkọ rẹ ti kọ ara wọn ti ọmọ ọdun mẹ́faa naa si n gbe lọdọ rẹ.

    Ṣadede ni o gbe ọmọ naa pamọ to si pe ọkọ rẹ lori ago pe awọn ajinigbe ti ji ọmọ naa gbe ti wọn si ti pe lati beere miliọnu mẹta naira owo idoola.

    ''O kan ṣadede pe ọkọ pe wọn ti ji ọmọ gbe ati pe awọn to jiigbe ti n beere miliọnu mẹta.Lẹyin ti ọrọ yi de eti igbọ wa la bẹrẹ iwadii to mu ki a ri ọmọ naa doola taa si gba mama rẹ mu''

    “Lọwọ bayii iwadii ṣi n tẹsiwaju''

    Kọmiṣana ọlọpaa Kano nibi to ti n ba obinrin naa ati ọmọ rẹ sọrọ

    Oríṣun àwòrán, Kano State Police Command

    Bawọn ọlọpaa ṣe n tẹsiwaju pẹlu iṣẹ wọn, bẹẹ ni nkan kayeefi mii tun ṣẹlẹ pẹlu bi ọkọ obinrin naa ṣe sọ pe oun yoo fẹ arabinrin naa pada.

    Eleyi jẹ nkan iyalẹnu fun ọpọ eeyan toun ti aṣemaṣe ti iyawo rẹ ṣe.

    O sọ fun BBC pe ''nkan ti ọpọ ko mọ ni pe ko tii ju ọjọ mejidinlọgbọn ti a kọ ara wa.Ikọraẹni silẹ naa ko ti fẹsẹ rinlẹ tan''

    ''Tori naa mo ri nkan to ṣẹlẹ yi gẹgẹ bi akọsilẹ.Ko ju bẹẹ lọ''

    O fi kun ọrọ rẹ pe ''lọwọ lọwọ bayii mo ti pinu lati fẹ iyawo mi pada ti a o si jọ gbe igbe alaafia gẹgẹ bi mọlẹbi pada''

    Ẹwẹ, Hafsa ti pada sile pẹlu baba rẹ ti iya rẹ to jẹ afurasi ṣi wa ni ahamọ ọlọpaa titi ti wọn yoo fi yanju ọrọ naa.

  7. Òkú èèyàn 29 lára ìjọ ṣọ́ọ̀ṣì alákatákítí ní wọn tún wù jáde nínú igbó

    Ileeṣẹ ọlọpaa Kenya ti wu oku eeyan mọkandinlọgbọn jade ninu igbo Kilifi lọjọ kan ṣoṣo.

    Awọn oku yi wa lara awọn mii ti wọn lo jẹ ti ọmọ ijọ ṣọọṣi alakatakiti kan ti oludasilẹ rẹ tan awọn ọmọ ijọ pe ki wọn febi panu ku bi wọn ba fẹ pade Ọlọrun.

    Nibi ọrọ de duro, wọn ti ri oku eeyan 179 bayii ti o jẹ ọmọ ijọ GoodNews International Church.

    Wọn ri apẹrẹ pe lara awọn eeyan wọnyi, awọn mii febi panu ku, wọn fun awọn mii lọrun tawọn mi si dero ọrun nipa pe wọn gba nkan mọ wọn lori.

    Bawọn agbofinro ati oniwadi ṣe n gbẹ ilẹ si, bẹẹ ni wọn n ri oku si .

    Koda ninu saare kan, oku mejila ni wọn ba ti wọn ko lori ara wọn sibẹ.

    Ajọ alagbelebu pupaa Red Cross ni Kenya sọ pe awọn ko mọ ibi tawọn eeyan 609 ọmọ ijọ ti Pasito Paul Mackenzie n dari ha si.

    Aworan awọn mọlẹbi to n daaro

    Oríṣun àwòrán, Reuters

    Pastor Mackenzie sọ pe lẹ́yin ọpọ ọdun oun pada ti ile ijọsin naa pa.

    Ṣugbọn iwadii BBC fi han pe ọkẹ aimọye iwaasu rẹ lo ṣi wa loju opo ayelujara.

    Pupọ ninu wọn lo gba silẹ lasiko to sọ pe oun ko ṣe ile ijọsin naa mọ.

    Ninu ifọrọwerọ kan to ṣe pẹlu ileeṣẹ iwe iroyin Kenya Daily Nation, Mackenzie sọ pe oun fi ipa mu ẹnikẹni lara awọn ọmọ ijọ rẹ lati gba awẹ doju iku.

    Iye awọ́n to di awati ninu ijọ rẹ ti to ilọpo mẹta lẹyin ti wọn bẹrẹ si ni gbẹ ilẹ ninu igbo ni ipari oṣu Kẹrin.

    Agbẹjọro agba ilẹ naa sọ pe lootọ lawọn kuna lati daabo bo awọn to farakasa ninu iṣẹlẹ yi.

    Olori ijọ alakatakiti yi ṣi wa ni ahamọ ọlọpaa.Wọn ko tii fi ẹsun kankan kan.

    Ile ẹjọ majistereeti kan ni Kenya lọjọ Iṣẹgun paṣẹ pe oun iyawo rẹ ati awọn eeyan mẹtadinlogun kan le na papa bora tori naa awọn ko le gba oniduro wọn.

    Agbẹjọro ijọba fẹ ki wọn fi Mackenzie si ahamọ fun aadọrin ọjọ ṣugbọn ọgbọn ọjọ pere ni adajọ yọnda fun un.

  8. Naijiria lorílẹ̀èdè kejì tí ikú aláboyún àti ògo wẹẹrẹ pòjù sí làgbáyé

    Iwadii tuntun ti ṣafihan pe orilẹede Naijiria ni orilẹede keji ni agbaye ti iku alaboyun ati ogo wẹẹrẹ pọju si julọ ni agbaye.

    Ajọ Iṣọkan Agbaye,UN gbe ọrọ yi jade ninu iwadii tuntun kan,ti o si ni orilẹede India jẹ eyi ti iku alaboyun ati ogo wẹẹrẹ ti pọju si julọ.

    Iwadii naa sọ pe ni ọdun 2020 ni India, laarin awọn eniyan 1000 to padanu ẹmi wọn, eniyan 788 ninu wọn lo jẹ alaboyun ati ogo wẹẹrẹ.

    Bakan naa ni wọn ni ninu eniyan 1000 to ku ni Naijiria ni ọdun 2020, eniyan 540 lo jẹ obinrin ati ogo wẹẹrẹ ninu wọn.

    Awọn orilẹede miran ti wọn tun kede pe o ni iku alaboyun ati ogo wẹẹrẹ to tun pọ ni the Democratic Republic of the Congo, Ethiopia, Bangladesh, China, Indonesia, Afghanistan, ati United Republic of Tanzania.

    Ninu ọrọ Minisita fun eto ilera, Osagie Ehanire, o ni iku awọn alaboyun naa ati ogo wẹẹrẹ ti ko tii pe ọmọ ọdun marun un ko ṣẹyin bi ko ṣe si eto iwosan to gbooro fun awọn araalu.

    Ajọ UN naa ni ajakalẹ aarun Covid-19, aisi owo ati eto igbayegbadun awọn eniyan to rẹyin ni agbaye lo fa ifaṣẹyin naa.

    Ajọ naa ni aarun Covid-19 mu ki ina eto ilera jo lajorẹyin, ti awọn obinrin ati ọmọde si wa n foju wina eto ilera ti ko munadoko.

    Wọn fikun un pe iye awọn alaboyun ati ọmọde to n ku lagbaye kọja bi o ṣe yẹ lọ.

    Adari ẹka eto ilera ni Unicef, Steven Lauwerie salaye pe lara ohun to n fa iku awọn ogo wẹẹrẹ ni bibi ọmọ lai ti pe iye ọjọ to yẹ.

    Wọn ni eyi ko ṣẹyin bi ko ṣe si eto iwosan pajawiri to peye ni awọn ile iwosan fun awọn ọmọ ti wọn ba bi ni aipe ọjọ.

    Aworan alaboyun

    Oríṣun àwòrán, Getty

  9. Ayálégbé dèrò ilé ẹjọ́ lẹ́yìn tó lu onílé rẹ̀ nílù bàrà nítorí owó iná

    Mita ina

    Oríṣun àwòrán, Getty Images

    Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko, ti gbe ọkunrin kan Usman Hammed lọ sile ẹjọ majistreeti kan lagbegbe Ogudu lori ẹsun pe o lu onile rẹ titi to fi dero ile iwosan.

    Iroyin nii ile wọn to wa ni adugbo Olaniyi, ni Agiliti, lagbegbe Mile 12, ni iṣẹlẹ naa ti waye niluu Eko.

    Ọlọpaa to gbe ẹjọ naa lọ iwaju adajọ, Donjor Perezi sọ fun ile ẹjọ ọhun pe afurasi naa wu iwa ọdaran naa lọjọ kẹjọ, oṣu Kẹrin, ọdun 2023 ni nnkan bii aago mẹsan an alẹ.

    Perezi fi kun pe ṣe ni afurasi naa lu onile rẹ niluu bara lẹyin ti obinrin ọhun bere owo ina mọnamọna to ti lo ṣaaju nile naa lọwọ rẹ.

    Gẹgẹ bii ohun to sọ, afurasi naa la ori onile rẹ mọ irin ilẹkun to wa niwaju ile wọn, eyii to mu ko dero ile iwosan.

    O fi kun pe ohun ti Hammed ṣe yii lodi si abala 173 ninu iwe ofin iwa ọdaran ipinlẹ Eko ti wọn gbe kalẹ lọdun 2015.

    Ẹwẹ, afurasi naa ti sọ pe oun ko jẹbi ẹsun ti wọn fi kan oun.

    Adajọ ile ẹjọ ọhun, Tanimola ti wa gba beeli rẹ bayii pẹlu owo ti iye rẹ jẹ ẹgbẹrun lọna ọgọrun naira pẹlu oniduro meji.

    Lẹyin naa lo sun igbẹjọ naa si ọjọ kẹrindinlogun, oṣu Karun un, ọdun 2023 yii.

  10. 10th NASS: Kà nípa ìlànà tí wọ́n fí n yan àwọn aṣáájú ilé aṣòfin ní Nàìjíríà

  11. Ìjọba fòfin dè kí àwọn òṣìṣẹ́ ọgbà ẹ̀wọ̀n máa yá 'tatoo' s'ára

    Aworan ẹlẹwọn to ya 'tatoo' si apa

    Oríṣun àwòrán, Getty Images

    Awọn oludari ileeṣẹ ọgba ẹwọn lorileede Namibia sọ pe awọn ti fofin de gbigba awọn eeyan to ba ni tabi ya tatoo si ara gẹgẹ bi oṣiṣẹ ọgba ẹwọn.

    Wọn ni awọn gbe igbesẹ yi gẹgẹ bi ọna ati daabo bo iṣẹ ọgba ẹwọn.

    Ileeṣẹ iroyin labẹle kan,Namibia Sun, jabọ pe niṣe ni ibẹru wa wi pe awọn oṣiṣẹ ọgba ẹwọn kan a maa ya iru tatoo to wa lara awọn ẹlẹwọn ti wọn n ṣọ sara.

    Ọga agba ileeṣẹ to n mojuto ọgba ẹwọn Raphael Hamunyella sọ pe iru aworan bayi lara ko ni jẹ kawọn eeyan maa foju rere wo ileeṣẹ awọn.

    Pupọ awọn aworan tatoo yi jẹ iru eleyi tawọn ikọ janduku maa n ya sara gẹgẹ bi ami idanimọ wọn.

    Tori eleyii, o ni awọn yoo mu iyipada ba eto igbanisiṣẹ ati ilana ihuwasi oṣiṣẹ ọgba ẹwọn ki wọn ma baa gba eeyan to ya tatoo sara sẹnu iṣẹ lọjọ iwaju.

    ''Tatoo tuntun lara yoo ṣokunfa ijiya labẹ ilana wa''

    Bẹẹ ni wọn ṣe sọ pe arakunrin Hamunyela sọ.

    O fi kun pe awọn yoo ṣe akọsilẹ orukọ awọn oṣiṣẹ ọgba ẹwọn to ba ya tatoo sara tori ọjọ iwaju.

  12. Amẹrika fúnra sí South Africa pé o n ṣatilẹyin nkán ìjà fún Russia

    Aworan aarẹ Ramaphosa South Africa

    Oríṣun àwòrán, Getty Images

    Orileede Amẹrika ti naka aleebu si South Afrika lori pe wọn lawọn furas si ilẹ naa pe o n ṣatilẹyin nkan ogun fun Russia ninu ikọlu Russia ati Ukraine.

    Aṣoju ilẹ naa ni eleyi n waye toun ti bi South frica ṣe ni awọn ko gbe lẹyin eyikeyi ninu awọn meji ti o n ba ara wọn ja yii.

    Ambassador Reuben Brigety sọ fun awọn akọroyin pe o da awọn loju pe wọn ko nkan ija si ọkọ oju omi Russia kan ni Cape Town loṣu kejila ọdun to kọja.

    Ninu esi rẹ, aarẹ South Africa Cyril Ramaphosa sọ pe awọn n ṣe iwadii ẹsun yi,

    Ẹwẹ, orileede naa ti tẹnumọ pe awọn ko gbe lẹyin ẹnikankan ninu ogun to n waye laarin Ukraine ati Russia.

    Lọjọbọ yi ni aṣoju Amẹrika Brigety sọ fawọn akọroyin pe ara n fu awọn pẹlu ẹjẹ South Africa pe awọn ko ni gbe lẹyin ẹnikankan ninu ikọlu Russia ati Ukraine.

    Ọrọ rẹ yi ko ṣẹ lẹyin ọkọ oju omi kan to ni o balẹ si ibudokọ ọkọ oju omi to wa ni Simon Town laarin ọjọ Kẹfa si ikẹjọ oṣu kejila ọdun to kọja.

    O ni o da awọn loju pe bo ṣe n ko nkan ija ogun, ''Russia ni wọn n gbe wọn lọ''

    Aworan afihan ọkọ oju omi Russia to balẹ si South Africa

    Oríṣun àwòrán, gett

  13. Ọwọ bá àwọn ajínigbépawó obìnrin tó n béèrè ọ̀pọ̀ mílíọ̀nù owó ìdóòlà

    Aworan awọn afurasi ajinigbe

    Oríṣun àwòrán, ABDULLAHI HARUNA KIYAWA/FACEBOOK

    Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Kano sọ pe awọn ti ribi mu awọn obinrin meji kan ti wọn fura si pe wọn pete pero lati ji awọn ọmọde kan gbe.

    Gẹgẹ bi wọn ṣe wi,ọkan ninu wọn pete lati ji ọmọ inu ara rẹ gbe ki o baa le ri owo idoola aimọye miliọnu gba lọwọ awọn obi ọmọ ti wọn ba ji gbe.

    Ninu awọn afurasi yi ni obinrin ẹni ọdun marundinlaadọta kan wa ti wọn fura si pe o wa lara awọn ikọ ẹlẹni mẹrin kan to ji ọmọ gbe ti wọn si beere owo idoola miliọnu marun un Naira.

    Atẹjade lati ọwọ agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa Abdullahi Haruna Kiyawa fẹsun kan obinrin naa to jẹ olukọ ọmọ taa n wi yi.

    O ni ero rẹ ni pe ko ji ọmọ naa Al Mustapha Bashir gbe ni ibẹrẹ oṣu to kọja.

    O ni ṣaaju awọn to ji ọmọ ọdun mẹfaa yi gbe ladugbo Kofar Ruwa ni Kano beere ogun miliọnu Naira lọwọ baba rẹ ki wọn to le tu silẹ.

    O tẹsiwaju pe baba ọmọ naa pada na owo naa walẹ ti wọn si gba miliọnu marun un Naira pẹlu ẹgbẹrun lọna aadọjọ Naira .

    "Lẹyin iwadii wọn ribi doola ọmọ naa ti ko si farapa.Ọwọ si tẹ ojulowo afurasi to pete pero bi wọn ṣe ji AlMustapha gbe''

    Yatọ si awọn wọnyii, ileeṣẹ ọlọpaa lawọn tun ri gbogbo awọn afurasi to lọwọ ninu ijinigbe ọmọdekunrin kan.

    O ni ọjọ ori awọn wnyi ti wọn wa lati agbegbe Sheka ko ju ọdun mẹrinlelogun si mẹtadinlọgbọn lọ.

    Bakan naa ni wọn lawọn ri opo kan ẹni ọdun marundinlọgbọn to ji ọmọ ọkọ rẹ tẹlẹ gbe to si beere miliọnu mẹta lowo ẹmi ọmọ naa.

  14. Nnamdi Kanu kò lè kú sí àtìmọ́lé – Ilé ẹjọ́ gíga jùlọ sọ̀rọ̀ bí wọ́n ṣe tún sún ìgbẹ́jọ́ rẹ̀ sí Òṣù Kẹ́sàn-án

  15. Ọmọdé méjì móríbọ́ lọ́wọ́ ikú lẹ́yìn tí wọ́n léfòó lórí omi àgbàrá fún ọjọ́ mẹ́ta

    Awọn ọmọ ti wọn doola

    Oríṣun àwòrán, KALEHE CIVIL SOCIETY

    Àwọn ọmọdé méjì kan móríbọ́ lọ́wọ́ ikú nígbà tí wọ́n ṣàwárí létí òkun Lake Kivu lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀ tí àgbàrá ṣekúpa ènìyàn tó lé ní irinwó lẹ́kùn ìlà oòrùn Democratic Republic of Congo.

    “Ohun ìyàlẹ́nu ló jẹ́ fún gbogbo wa” adarí ìlú, Delphin Birimbi sọ fún BBC.

    Birimbi ní àwọn òbí àwọn ọmọ náà ti kú àmọ́ àwọn ti ń bá àwọn tó lè ṣe ìtọ́jú àwọn ọmọ ọ̀hún sọ̀rọ̀.

    Bí àwọn ọmọ náà ṣe yé lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n lò lórí omi àmọ́ àwọn tó ṣàwárí ní àwọn rí wọn tí wọ́n léfòó lórí àwọn ìdọ̀tí tó wà létí omi náà.

    Birimbi ní ọjọ́ Ajé ni wọ́n rí àwọn ọmọ náà yọ, ọ̀kan ní Bushushu, tí wọ́n sì rí ìkejì ní Nyamukubi, àwọn ìlú méjèèjì tí àgbàrá òjò ńlá ti ṣọṣẹ́ ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá.

    Àjọ Red Cross orílẹ̀ èdè Congo ní ìṣẹ̀lẹ̀ omíyalé yìí ti fa kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀mí sùn tí ominú sì ń kọ àwọn lórí bí òórùn àwọn òkú tó ti ń jẹrà ṣe gbòde.

    Ọ̀pọ̀ òkú ni wọ́n tún ṣe àwárí rẹ̀ nínú irà lọ́jọ́rú èyí sì ti jẹ́ kí ènìyàn tó ti kú ti wọ 411 báyìí.

    Nínú àwọn wọ̀nyí, 317 òkú ni wọ́n ti sìn.

    Àwọn olórí ìlú agbègbè náà ní ó ṣòro láti dá òkú àwọn ènìyàn tó pàdánù ẹ̀mí wọn mọ̀ tán nítorí púpọ̀ nínú àwọn tó kú náà ló kàn wá ná ọjà kí òjò ńlá tó ká wọn mọ́ ibẹ̀.

    Agbenusọ àjọ Red Cross ní DR Congo, John Kashinzwet sọ fún BBC pé látàrí bí kò ṣe sí ilé ìgbókùúpamọ́sí ńlá ní agbègbè náà, sínsin àwọn òkú náà láìpẹ́ ló yẹ ní kété tí àwọn ènìyàn wọn bá ti rí wọn.

    Nínú fídíò kan tí akọ̀ròyìn kan fi sórí Twitter, obìnrin kan ń sọ níbẹ̀ pé ọ̀kan nínú àwọn ọmọdé náà ti fi ẹsẹ̀ ṣèṣe.

    Birimbi ní ènìyàn tí àwọn ṣì ń wá lé ní ẹgbẹ̀rún márùn-ún báyìí àti pé iṣẹ́ ṣì ń lọ láti ṣàwárí wọn.

    Kò dín ní ènìyàn igba tó farapa ni ìròyìn ní wọ́n wà ní ilé ìwòsàn níbi tí wọ́n ti ń gba ìtọ́jú látàrí omíyalé ọ̀hún.

    Ilé ìgbé 1,300, ọ̀pọ̀ ilé ẹ̀kọ́, ilé ìwòsàn, ilé ìjọsìn àti omi ló ti bàjẹ́.

    Gentile Ndagijimana sọ fún BBC gbogbo nǹkan òun ni àgbàrá náà ti gbé lọ.

    “Mi ò ní nǹkankan mọ́, kò sí ẹbí, ọkọ, gbogbo ẹ ni àgbàrá ti gbà lọ.”

    Birimbi wá ní láti ìgbà tí àjálù náà ti wáyé, ìjọba pàápàá Ààrẹ àti Mínísítà kankan kò yọjú sí ibẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n kéde ọjọ́ Ajé láti fi ṣe ìdárò àwọn tó pàdánù ẹ̀mí wọn.

    Àgbàrá òjò yìí ló ń wáyé lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀ tí ìṣẹ̀lẹ̀ omíyalé àgbàrá ya ṣọ́ọ̀bù ṣekúpa ènìyàn tó lé ní 130 ní Rwanda.

    Ọ̀gá àgbà àjọ ìṣọ̀kan àgbáyé Antonio Guterres ní àwọn omíyalé yìí ń wáyé látàrí àyípadà ojú ọjọ́.

  16. Dókítà àgbà fipá bá aláìsàn lòpọ̀, ilé ẹjọ́ ní kó lọ máà gba afẹ́fẹ́ lẹ́wọ̀n

  17. Àwọn òṣèré tíátà tó lọ́ ń fi arúgbó ara kàwé síì, ohun tí wọn yóò mú bá agbo sinimá nìyí – Tunde Kelani

  18. Eze Ndigbo tó ní òun yóò fìwé pe IPOB wá sí Eko fojú balé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ìgbésùmọ̀mí

  19. Ìlànà 'zoning' ipò aṣáájú ilé aṣòfin tí ẹ gbé kalẹ̀ kò bójú mú-Akeredolu

    Aworan Gomina Akeredolu

    Oríṣun àwòrán, Facebook/Rotimi Akeredolu Aketi

    Gomina ipinlẹ Ondo ti darapọ mọ awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC to tako ilana ti ẹgbẹ gbe kalẹ lati fi pin iyansipo awọn ti yoo dije ipo aṣaaju ile aṣofin.

    Akeredolu ninu atẹjade kan to fi sita sọ pe ilana yi ku diẹ kaato ati pe o tubọ fẹsẹ aiṣedeede rinlẹ si ni.

    Akeredolu ti o jẹ ọkan lara awọn Gomina eekan ninu ẹgbẹ APC ṣalaye pe o ku diẹ kaato pe agbegbe ila oorun ariwa nikan ni yoo ko meji ninu ipo mẹrin tawọn iyoku ko si ni ni ipin ninu rẹ.

    O ni ''igbesẹ lati dari awọn ipo yi lọ si ọdọ agbegbe kan lati ọwọ awọn ti wọn ro pe awọn sunmọ aarẹ foju jọ didẹ takute kalẹ to si tun n fi ẹsẹ aigba ara ẹ ni gbọ lelẹ.O yẹ ka yago fun eleyi ni''

    O ni ohun ti ko bojumu ni pe awọn alaṣẹ ẹgbẹ ko kan si awọn oludije ipo olori ile aṣofin ki wọn to gbe igbesẹ yi.

    Akeredolu wa gboṣuba kaare fawọn oludije ipo olori ile aṣojuṣofin lori bi wọn ṣe panupọ lati bẹnu atẹ lu igbesẹ igbimọ alaṣẹ ẹgbẹ.

    O rọ awọn alaṣẹ ẹgbẹ lati tọ oju ọna iṣedeede.Bakan naa lo sọ pe oun lero pe Bola Ahmed Tinubu ti wọn yan sipo aarẹ yoo toju bọ ọrọ yi ki o si tọ ọmọ ẹgbẹ sọna to tọ ati to yẹ.

    Bola Tinubu ko si lorileede Naijiria bayii latari irinajo to ṣe lọ silẹ okere.

    Fakinfa awọn ti yoo du ipo aṣaaju ile yi jẹ nkan tawọn onwoye n sọ pe o le da wahala silẹ fun ẹgbẹ APC nigba ti wọn yoo ba fi ṣe idibo yan awọ́n olori yi fun ile aṣofin Naijiria.

  20. Ipò aṣáájú ilé aṣòfin tí APC pin, wo ìdí tàwọn ọmọ ẹgbẹ́ kàn ṣe takò

    Aworan Senetọ Akpabio ati  Ahmed Wase

    Oríṣun àwòrán, Facebook/Godswill Obot Akpabio/Ahmed Wase

    Igbakeji olori ile aṣojuṣofin Naijiria ti kọ iwe kotẹmilọrun lori igbesẹ ẹgbẹ rẹ, APC, lati pin awọn ipo aṣaaju ile sawọn agbegbe kan ni Naijiria.

    Ahmed Idris Wase ati awọn oludije mii fun awọn ipo wọnyi nile aṣojuṣofin ati ile aṣofin agba ti pawọpọ fi iwe ẹdun ọkan ranṣẹ si olu ile iṣẹ ẹgbẹ APC ni Abuja ti wọn si ni ki ẹgbẹ yi ipinnu yi pada.

    O fidi ọrọ yi mulẹ lasiko to n ba awọn akọroyin sọrọ ni kete to fi iwe yi lelẹ.

    Igbesẹ Ahmed ati awọn oludije mii yi n waye lasiko ti igbimọ alaṣẹ ẹgbẹ wọn n ṣe ipade pajawiri lori awuyewuye awọn ti wọn yoo yan sipo aṣaaju ile aṣofin kẹwaa yi.

    Lọjọ Aje to kọja ni ẹgbẹ APC fi atẹjade kan sita pe awọn ti panupọ lati pin awọn ipo aṣaaju yi laarin awọn igun kan lorileede Naijiria.

    APC sọ pe igbimọ tẹẹ ko to ẹgbẹ ti buwọ́lu atilẹyin Sẹnẹtọ Godswill Akpabio gẹgẹ bi oludije ipo aarẹ ile aṣofin agba nigba ti wọn si lawọn ṣatilẹyin fun Tajudeen Abbas gẹgẹ bi olori ile aṣojuṣofin.

    Awọn onwoye agbo oṣelu Naijiria ti wa n sọ pe o ṣeeṣe ki igbesẹ yi mu iyapa wa laarin awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC ati awọn ọmọ ẹgbẹ to n du ipo yi nile aṣofin kẹwaa ti yoo gbera sọ ni Naijiria.