You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Obìnrin ẹni ọdún 45 gbé ọkọ rẹ̀ lọ ilé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé kò mú òun lọ Saudi Arabia
Obinrin ẹni ọdun marundinlaadọta kan, Karima Nuhu ti gbe ọkọ rẹ, Musa Falalu, lọ sile ẹjọ kan nipinlẹ Kaduna lori ẹsun pe o kọ lati mu oun lọ si Saudi Arabia.
Karima, to n fi agbegbe Rigasaa niluu Kaduna ṣebugbe sọ fun ile ẹjọ naa pe ọdun mẹrin lawọn fi wa gẹgẹ bii tọkọ-taya, ṣugbọn oṣu meji pere lo fun oun lounjẹ.
O tun sọ fun ile ẹjọ ọhun pe ọkunrin naa lu oun ni jibiti, to si gba gbogbo owo ọwọ oun pata, lẹyin eyii ti o kọ oun silẹ.
O ni “O sọ fun mi pe oun padanu iṣẹ oun gẹgẹ bii awakọ amọ oun riṣẹ mii lorilẹ-ede Saudi Arabia, to si bẹbẹ pe ki n ni suuru pẹlu ileri pe oun yoo mu mi lọ sọhun.”
“Lati igba naa wa, emi ni mo n bọ ara mi, koda mo tun n ya owo fun paapaa lara owo ti mo fi pamọ ko le mu mi lọ si irinajo ọhun amọ lẹyin to gba gbogbo nnkan to fẹ gba lọwọ mi tan, o kọ mi silẹ.”
Nigba ti ilẹ ẹjọ bere lọwọ rẹ boya o ni ẹlẹri, o ni “Mi o ni ẹlẹri kankan ayafi Ọlọrun ti yoo ṣedajọ gbogbo wa ni ikẹyin.”
Amọ olujẹjọ ti fesi pe irọ ni gbogbo nnkan ti obinrin naa sọ fun ile ẹjọ.
O fi kun pe oun ti kọ obinrin naa silẹ ṣaaju igbẹjọ ọhun.
Adajọ Anass Khalifa to gbọ ẹjọ naa fidi ikọsilẹ tọkọ-taya ọhun mulẹ, lẹyin naa lo ni oun ko ni gbọ ẹjọ naa mọ ayafi ti olupẹjọ ba mu ẹlẹri wa.
Lẹyin naa lo wọgile si igbẹjọ ọhun.