Akẹ́kọ̀ọ́ FGC Yauri mẹ́ta pàdánù ẹ̀mí wọ́n nígbà t'awọn ológun àti ajínigbe kojú ará wọ́n

Awọn to ba BBC sọrọ sọ pe ninu ikọlu to waye laarin awọn agbebọn yi ati ọmọogun Naijiria ni awọn ọmọ yi ti padanu ẹmi wọn.

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Yetunde Olugbenga and Yemisi Oyedepo

  1. Wo bí ìséde tí ìjọba ìpínlẹ̀ Osun kéde yóò ṣe lọ

    Gomina ipinlẹ Osun

    Oríṣun àwòrán, TWITTER/ ADEGBOYEGA OYETOLA

    Gomina ipinlẹ Osun, Gboyega Oyetola ti kede isede jakejado ipinlẹ naa.

    Ninu ikede kan to fi sita lori ayelujara Facebook rẹ, Akọwe iroyin ati ikede fun gomina, Ismail Omipidan sọ pe loju ẹsẹ ni isede naa ti bẹrẹ.

    Bakan naa lo sọ fun BBC pe alainigbedeke ni isede naa yoo jẹ.

    O ni eyi waye nitori bi awọn janduku kan ṣe n kọlu awọn dukia ijọba, ati awọn ileeṣẹ ati ṣọọbu aladani lati ji wọn ni ẹru ko.

    "Ijọba gbe igbesẹ yii lati ma le fi opin si iwa ti awọn janduku n hu, ati lati ri i daju pe wọn ko ba nkan jẹ kọja bi o ṣe yẹ."

    Isede naa yoo ma a wa fun lati aarọ di alẹ.

    Igba keji niyii ti ijọba ipinlẹ naa kede konile-o-gbele lati igba ti iwọde #EndSars ti bẹrẹ, ati rogbodiyan to tẹle.

  2. Ẹ wo ojú àwọn jàndùkú tí ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ nígbà tí wọ́n lọ kó ọjà ọlọ́jà ní Shoprite Ilorin

  3. Èròjà oúnjẹ Covid-19 tẹ kó nílé ẹ̀rù, aládàníi ló ní, kìí ṣe àwa - Ìjọba Oyo, EndSARS Protest Updates: Ìjọba Oyo kéde pé èròjà Covid-19 táráàlú kó, kìí ṣe tòun

    Ijọba Ipinlẹ Oyo ti fesi si iroyin kan to gba ode wipe, awọn ko awọn ounjẹ ti wọn pese lati dena iyan nipasẹ ti arun COVID-19 pamọ nitori iwa imọ taraẹni.

    Ijoba ipinle Oyo ti wa salaye wipe ahesọ ọrọ lasan ni eyi jẹ, to si fi idi rẹ múlẹ pe ontaja aladani kan lo ni awọn ẹru naa.

    Ijọba ipinlẹ Oyo sisọ loju ọrọ naa, nigba to n sọrọ lori bi awọn janduku ṣe jawọ ile ikẹrusi aladani kan to wa ni adugbo Akobọ n'ilu Ibadan, tí wọn si ko ọpọlọpọ apo iresi ati awọn ounjẹ orisirisi miran lọ.

    Kọmisọna fọrọ ijoba ibilẹ ati alaga fun eto ounjẹ pinpin ni Ipinlẹ Oyo, Oloye Bayo Lawal, nigba ti o n yanana ọrọ yii ṣalaye wipe, ẹnikan to n sisẹ pelu ajọ to n risi idena arun COVID-19 (CACOVID) lo ni ile ikẹrusi naa, laini nkankan ṣe pẹlu ijọba ipinlẹ Oyo.

    Awọn eroja tara ilu gbe lọ

    Oríṣun àwòrán, OYSG

  4. Òkú ọ̀dọ́ 15 ni mo kà ní Lekki amọ́ mo kábàámọ̀ pé a gbà kí ológun gbé okù wọn lọ - DJ Switch

  5. Ẹ wo ọ̀rọ̀ àwọn Wòlíì tó ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ saájú nípa làásìgbò EndSARS

  6. Májèlé olóró lẹ gbé l‘Ekiti dípò èròjà oúnjẹ Covid-19 - Ariwo sọ lórí ayélujára

  7. Buhari kò láànú ọmọ Nàìjíríà lójú - Aisha Yesufu

  8. Àìsọ̀rọ̀ Buhari lórí ìṣẹ̀lẹ̀ Lekki, ìkọjú ìjà sí Yoruba ni - YWC

  9. ₦147m la rí kójọ fún ìwọ́de, a kò fẹ́ owó mọ́, ìwọ́de ti parí - Feminist Coalition

  10. Ìwọ́de EndSARS kìí ṣe ọ̀rọ̀ ẹlẹ́yàmẹ̀yà, ara ti kan àwọn èèyàn ni - Afenifere

  11. Wo ìyàtọ̀ tó wà láàrin Àjọ, Àáró àti ọ̀wẹ̀, tí wọn jẹ́ àṣà ìran ara ẹni lọ́wọ́ nílẹ̀ Yorùbá

  12. Kò sí rògbòdìyàn tó lè sẹlẹ̀ ju wákàtí 24 lọ láì ní ọwọ́ ìjọba níbẹ̀- Ogagun Ibrahim Babangida

  13. Àwọn ọlọ́jà ń sèdárò Ìyálọ́jà ìpínlẹ̀ Oyo tó dolóògbé, wọ́n yan asojú míràn

  14. Tani Oke Obi-Enadhuze: tí orúkọ rẹ̀ gba orí ayélujára kàn lẹ́yìn wàhálà #Lekki tollgate?

  15. Àwọn jàndùkú kọlu ọgbà ẹ̀wọ̀n Ikoyi, agbófinró gba àkóso ibẹ̀

  16. Ilẹ̀ Amẹ́ríkà wà lẹ́yìn àwọn olùwọ́de, Buhari dẹ́kun ìpànìyàn - Joe Biden

  17. Buhari, máṣe gbá ìpànìyàn Lekki sórí ààtàn, kò yẹ́ kí ológun yin ọ̀dọ́ níbọn - Bode George

  18. Èèyàn 300 ló pè mí láti mọ̀ bóyá ìbọn bà mí ní Lekki - Eniola Badmus

  19. Ìbọn ń dún kíkan n‘Ibadan, àwọn òǹtàjà ti ṣọ́ọ́bù pa

  20. Ìpínlẹ̀ Ogun náà ti ilé ìwé títí dí ọjọ́ Ajé tó m bọ̀, kò ní sí lílọ bíbọ̀ ọ̀kádà fún wákàtí 24