You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.

Take me to the main website

Ọ̀pọ̀ èèyàn di àwátì lẹ́yìn tí ọkọ̀ ojú omi ńlá kọlù afárá l’Amẹrika

Akojọpọ awọn iṣẹlẹ kaakiri agbaye

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

Olumide Owaduge and Olubusola Afolayan

  1. Kò dín ní 7,000 èèyàn tó ha ́sí ẹnubodè Egypt lẹ́yìn tí ogun lé wọn kúrò ní Sudan – Ìjọba àpapọ̀

    Ijọba Naijiria ti sọ pe ko din ni ẹgbẹrun meje eeyan to ti ha si ẹnubode orilẹ-ede Egypt bayii lẹyin ti ogun le wọn lati Sudan.

    Alaga ajọ to n ri si ọrọ ọmọ Naijiria nilẹokeere, NIDCOM, Abike Dabiri-Erewa lo fi ọrọ naa lede.

    O ni awọn eeyan naa, ti ọpọ ọmọ Naijiria wa lara wọn ni wọn ha si ẹnubode Egypt, ti wọn ko si ri aye lati wọn ilẹ naa.

    Ninu atẹjade kan ti alukoro NIDCOM, Gabriel Odu, fi lede, o ni ipo ti awọn eeyan naa wa n kọ ijọba Naijiria lominu.

    Atẹjade naa ni “Dabiri-Erewa sọ pe o le ni ẹgbẹrun meje eeyan, ti awọn ọmọ Naijiria walara wọn, ti wọn ko gba laaye lati rekọja wọ orilẹ-ede Egypt lẹnubode ilẹ naa lati igba ti wọn ti wọn ti de ibẹ lati alẹ ana.”

    Ọọfisi ijọba Naijiria ni Egypt ti n ṣiṣẹ takuntakun lati ri pe awọn eeyan ọhun rekọja si Egypt amọ ijọba Egypt n sọ pe awọn to ba fẹ wọ ilẹ awọn gbọdọ ni iwe irina lọwọ.

    “O ti wa rọ ijọba Egypt lati fun awọn eeyan naa lanfani lati gba ilẹ rẹ kọja ki wọn le pada si orilẹ-ede wọn lai si idiwọ kankan.”

    Iṣẹlẹ yii lo n waye lẹyin ti minisita ọrọ ilẹ okeere, Geoffrey Onyeama, kede pe ijọba Naijiria ti ya ọkọ akero ogoji ni owo iye rẹ to $1.2m lati fi ko awọn ọmọ Naijiria to ha si Sudan kuro nibẹ lọ si Egypt ki wọn le pada wale.

  2. Ẹ gbárùkù ti Tinubu - Makinde, Wike rọ àwọn ọmọ Nàìjíríà

    Gomina Nyesom Wike ti ipinlẹ Rivers ti rọ àwọn ọmọ orilẹede Naijiria lati gbarukuti aarẹ tí ilu sẹsẹ dibo yan, Bola Tinubu.

    Wike ni eto idibo tí wa sopin fun idi eyi Tinubu nilo atilẹyin lati ṣe ìjọba ti awọn araalu fẹ.

    O sọrọ yii lasiko to n ba awọn akọroyin sọrọ lẹyin to ṣe ipade pọ pẹlu Tinubu niluu Abuja.

    Wike, ẹni to kọwọrin pẹlu ajẹgbẹ lati ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde.

    "Eto idibo tí wa, o si ti lọ ati mọ ẹni to borí fun idì eyi asiko ti to lati gbarukuti ti aarẹ tuntun.

    "Gbogbo wa ni a n duro de ọjọ Kọkandinlọgbọn fun eto ibura aarẹ tuntun, to si damiloju pe o ni gbogbo nkan lati mu ayipada ba orilẹede Naijiria."

    Nigba ti o n sọrọ, Gomina Seyi Makinde ni oun setan lati gbarukuti aarẹ tuntun fun ilọsiwaju orilẹede Naijiria.

    "Mo wa si ibi bayi loni lati wa kan sara si aarẹ tuntun ati lati jẹ ko mọ pe eto idibo tí wa sopin, i ṣe ìjọba rere loku.

    "Gbogbo ipa wa ni a lo lati se atilẹyin fun Tinubu fun ìjọba rere."

  3. Tí o bá fẹ́ di gómìnà Kogi, kàn sí àwa Àjẹ́ àti Oṣó .....Oboi

  4. A kò ní yọ ìrànwọ́ orí epo bẹntiróòlù lóṣù Kẹfà mọ́- Ìjọba àpapọ̀

  5. 'Mi ò lọ sí ilé ẹ̀kọ́ kankan ẹ̀bùn tí Ọlọ́run fún mi ni mo fi ń ṣe ọkọ̀ òfurufú'

  6. Àlàyé rèé lórí ogun tó ń wáyé ní Sudan táwọn ènìyàn fí ń sá kúrò níbẹ̀

  7. Níbo lẹ ti gbọ́ pé mo kọ ọkọ mi sílẹ̀ ló fẹ́ Pasuma?, Bí ọ̀rọ̀ ìfẹ́ èmi àti Paso ṣe bẹ̀rẹ̀ rèé- Jaye Kuti

  8. Ijoba Ogun ṣèkìlọ̀ fáwọn ìlú 23 láti kó kúrò nítorí omíyalé agbára yọ ṣọ́ọ̀bù

    Awọn olugbe agbegbe Mowe, Isheri, Akute, Ibafo, Riverside ati awọn agbegbe miiran to wa laarin ipinlẹ Eko si ipinlẹ Ogun ni wọn ti gba ni mọran lati ko kuro ni agbegbe naa nitori ẹkun omi yale.

    Ìjọba ipinlẹ Ogun lo gba wọn niyanju bẹẹ ninu atẹjade ti kọmisọna fun ayika nipinlẹ Ogun, Ola Oresanya fi ransẹ si awọn akọroyin.

    Ìjọba ni o se pataki fun awọn olugbe lati ko kuro ni awọn agbegbe nitori ki ijamba miiran maa tun le waye.

    Oresanya ni kí awọn olugbe agbegbe maa reti ọpọlọpọ ẹkùn omi laarin oṣu kẹrin si oṣu kọkanla.

    Bakan naa ni Oresanya tu wa rọ awọn agbẹ láti jara mọ ṣe lati maa fun omi yale ni anfani lati se ijamba.

    Awọn agbegbe miiran ti ìjọba kede ni Onikoko, Sokori ati Arakanga niluu Abeokuta; Isaka Owode ni Ado-Odo Ota; Ebute Kimobi ni Ijebu, Owa ati Yemule ni Ijebu-Ode; Eruwuru ni Sagamu; Owode, Igijo, Ilaro ati Ijoko

  9. Ṣé lóòótọ́ ni NBA jáwé lọ rọ́kún nílé fún agbẹjọ́rò tó ń fa igbó lórí ayélujára?

  10. Olupele ti ìlú Ipele, Ọba Victor Aganun tẹri gbaṣọ

  11. Ọ̀pọ̀ Ọba tó ń gbé ẹ̀sìn Krìstẹ́nì àti Islam sórí ní gbangba, ló ń bá òrìṣà jẹ ní kọ̀rọ̀- Bàbá Osun Osogbo

  12. Portable tún fojú balé ẹjọ́ lónìí, ibi tí ìgbẹ́jọ́ dé dúró lórí ẹ̀sùn mẹ́fà tí wọ́n kà si lọ́rùn nìyí

  13. EFCC wọ́ abẹnugan Ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ondo lọ ilé ẹjọ́

    Ajọ to n gbogun ti iwa ijẹkujẹ atawọn iwa ibajẹ miiran to n se akoba fun ọrọ aje, EFCC ti wọ abẹnugan ile asofin ipinlẹ Ondo, Rt Hon Bamidele Oloyeloogun lọ siwaju ile ẹjọ giga niluu Akure.

    Abẹnugan ọhun ati awọn meji ni EFCC fẹsun kan wọn lu owo ni ponpo, eyi ti wọn ni awọn ko jẹbi rara.

    Agbẹjọro EFCC, Kingsley Kudus wa rọ ile ẹjọ lati fi awọn afurasi naa satimọle ti ti igbẹjọ yoo fi pari.

    O ni tori pe awọn afurasi naa ni awọn ko jẹbi ẹṣun ko ni pe ki wọn ma lọ ni alaafia lasiko ti igbẹjọ sí n lọ lọwọ.

    Ṣugbọn Agbẹjọro awọn olujẹjọ, Barr. Femi Enodamori ni ki ile ẹjọ wogile ipe akẹgbẹ rẹ, to si bẹ bẹ fun itusilẹ fun awọn afurasi naa.

    Adajọ Adegblyega Adebusoye wa sun Igbẹẹjọ siwaju, ọjọ kejìdínlógún, osu karun un, to si fun awọn afurasi ni anfani lati ma jẹjọ lati ile.

  14. Àarẹ Joe Biden kédé pé òun yóò díje du ipò fún sáà kejì gẹ́gẹ́ bí ààrẹ ilẹ̀ Amẹrika

    Aarẹ ilẹ Amẹrika Joe Biden ti kede pe oun yoo dije du ipo aarẹ fun saa keji ni ọdun 2024.

    O ṣeeṣẹ ki aarẹ Joe Biden figagbaga pẹlu aarẹ tẹlẹ, Donald Trump.

    Ninu fidio to fi lede lọ ti fi igbiyanju rẹ lede lati dije du ipo aarẹ lẹẹkan si.

    O ni eyi pọn dandan nitori oun ni lọkan lati jẹ ki orilẹede Amẹrika tubọ maa goke agba si lai wẹyin.

    Igbakeji aarẹ, Kamala Harris naa to jẹ ẹni ọdun mejidinlọgọta naa ni oun yoo maa dije du ipo pẹlu Joe Biden.

    Nibayii, aarẹ Biden to jẹ ẹni ọgọrin ọdun ni aarẹ to dagba julọ ni itan ilẹ Amẹrika, to si ṣeeṣe ki awọn eniyan tọka si ọjọ ori rẹ lasiko ipolongo idibo naa.

    Ti o ba wọle fun saa keji, yoo jẹ ẹni ọdun mẹrindinlaadọrun nigba to ba pari ni ọdun 2029.

    Awọn aarẹ marun un ti wọn dagba julọ ni itan ilẹ Amẹrika rèé

    Ọpọlọpọ awuyewuye lo ti jẹyọ lẹyin ti aarẹ ilẹ Amẹrika kede pe oun lọ fun saa keji lẹni ọgọrin ọdun.

    Oun ati Donald Trump to aarẹ keji to dagba julọ lagbaye ni wọn yoo jọ maa dije du ipo aarẹ ni ọdun to n bọ.

    Awọn aarẹ marun un ti wọn dagba julọ ni itan Amẹrika ree...

    • Joe Biden lo dagba ju ni ọdun 2021 lẹni ọdun 78
    • Donald Trump lo jẹ ẹnikeji to si di ipo aarẹ mu lati ọdun 2017 lẹni ọdun 70
    • Ronald Reagan lo di ipò aarẹ mu ni ọdun 1985 lẹni ọdun 69
    • William Henry Harrison lo jẹ aarẹ ni ọdun 1841 ni ẹni ọdun 68 to si ku lẹyin oṣu kan
    • James Buchanan lo dipo aarẹ mu ni ọdun 1857 lẹni ọdun 65.
  15. Ènìyàn kan kú, ọ̀pọ̀ farapa bí àwọn afurasí darandaran ṣe ṣèkọlù sáwọn àgbẹ̀ ní Ondo

  16. Irọ̀ ní, a kò tíì kéde Aláàfin tuntun - Ìjọba Ìpínlẹ̀ Oyo

  17. Wo ọ̀nà láti gbógun ti àìsàn Ibà lásìkò yìí

  18. Kokoko lára mi le, àláfíà ni mo wà - Tinubu

    Aarẹ ti ilu sẹsẹ dibo yan, Bola Ahmed Tinubu ti laakọ ni ara oun wa, ti alaafia to peye si wa pẹlu oun saaju ibura rẹ gẹgẹ Aarẹ orilẹede Naijiria.

    Saaju ni ọpọlọpọ iroyin ti gba ori ayelujara pe Tinubu ṣe arẹ ni o fi kuro lorilẹede Naijiria lọ si oke okun.

    Tinubu sọ eleyi ni ile rẹ ni Asokoro niluu Abuja kete to pada de lati orilẹede France.

    O pada si orilẹede Naijiria pẹlu iyawo rẹ, Sẹnẹtọ Oluremi Tinubu, ti igbakeji aarẹ tuntun, Kashim Shettima, Gomina Ipinlẹ Plateau, Simon Lalong, Agbẹnugan ile asofin, Femi Gbajabiamila pẹlu awọn eeyan jakanjakan si lọ ki wọn kaabọ.

  19. Tottenham gbaṣẹ́ lọ́wọ́ akọ́nimọ̀ọ́gbá wọn, Christian Stellini

    Ẹgbẹ agbabọọlu Tottenham ti fi ọwọ osi juwe ile fun akọnimọgba wọn, Christian Stellini, lẹyin ọsẹ mẹta tí wọn gba sisẹ.

    Ọpọ lo ìgbagbọ pe awọn alasẹ ẹgbẹ agbabọọlu gbe igbesẹ naa lẹyin tí ikọ Newcastle lu Tottenham ni ilu iya, ami ayo mẹfa si ẹyọ kan lọjọ Satide.

    Alaga ẹgbẹ agbabọọlu Tottenham, Daniel Levy ni esi ifẹsẹwonsẹ naa lo dojutini, ti ko si ni itẹwọgba rara.

    Stellini ni wọn kede lọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu kẹta lẹyin ti wọn gba isẹ lọwọ Antonio Conte.

    Bayìí, Ryan Mason, agbabọọlu tẹlẹ fun ikọ naa ni yoo ma tukọ ẹgbẹ agbabọọlu naa ti saa yoo fi parí

  20. Àwọn orílẹ̀èdè tó tí kó àwọn ènìyàn wọn kúrò ní Sudan rèé

    Ọpọlọpọ orilẹede lo ti n ko awọn eniyan wọn kuro ni Sudan bayii lẹyin ti ija laarin awọn ọgagun naa wọ ọṣẹ keji.

    Nkan bii ọṣẹ meji ṣẹyin 1 ni ija bẹ silẹ ni Khartoun laarin awọn ọgagun meji ti wọn n tako ara wọn gẹgẹ bi adari lorilẹede naa.

    Igun ikọ ọmọogun to gbajọba lo n koju ikọ RSF to n lọgun lati gba ijọba.

    Iye orilẹede to ti ko awọn eniyan wọn kuro niyii

    • Ọjọ Aiku ni orilẹede Amẹrika, Canada ati Ilẹ Gẹẹsi kede pe awọn n ko awọn eniyan wọn kuro ni Sudan.
    • Aarẹ ilẹ Faranse, Emmanuel Macron kede pe Ọjọ Aiku ati Ọjọ Ajẹ ni awọn yoo gbe awọn eniyan wọ̀n to le ni 388 kuro nibẹ.
    • Bakan naa ni orilẹede Belgium ni awọn ti ko awọn eniyan wọn ni ilu Kahrtoum pẹlu ọkọ ofurufu ilẹ Farance.
    • Ijọba Ilẹ Gẹrman ni ọkọ ofurufu mẹta ti kuro ni Sudan lọ si Jordan fun aabo awọn ẹniyan mọkanlelọgọrun to wa ninu baalu naa.
    • Italy, Spain naa ni awọn ti kọ awọn eniyan wọn kuro to fi mọ awọn ọmọ ilẹ Argentina, Colombia, Portugal, Poland, Mexico, Venezuela ati Sudan.
    • Turkey fi ọkọ ko awọn eniyan to le ni ẹgbẹta lati gba oju ọna kuro ni Sudan pẹlu awọn eniyan lati orilẹede Azerbaijan, Japan, China , Mexico ati Yemen.