Àwọn agunbanirọ ti ko awọn ohun eelo kuro lọ si ibudo idibo ni Bayelsa, Iṣẹ eto idibo ti bẹrẹ ni kikun ni ipinlẹ Bayelsa
Awọn agunbanirọ lọkunrin lobinrin ni wọn n sin ilẹ Baba wọn nipa kikopa ninu eto idibo to n lọ lọwọ ni bayelsa
Ẹ kaabọ si oju opo BBC Yoruba. Wọnyii ni ohun ti awọn akọ̀ròyìn wa to ti wa ni ikalẹ ni ipinlẹ Kogi ati Bayelsa.
Yetunde Olugbenga
Awọn agunbanirọ lọkunrin lobinrin ni wọn n sin ilẹ Baba wọn nipa kikopa ninu eto idibo to n lọ lọwọ ni bayelsa
Agbegbe Attah Frontage ti ibudo idibo yii wa ni Lokoja ni ọpọ ero ti to lọwọọwọ wa yan ẹni ti ọkan wọn fẹ.



Awọn awakọ n ba iṣẹ oojọ wọn lọ ni opopona Kogi


Bukola Saraki to jẹ aarẹ ile igbimọ Aṣofin Naijiria tẹlẹ ti gba awọn oludibo ni imọran lati ṣọra ṣe ki wọn wa ni alaafia.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Awọn eniyan Okenne ti bẹrẹ idibo ni pẹrẹwu- INEC
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Awọn oludibo ti bẹrẹ si ni tẹka foludije to wu wọn ni ilu Gomina Yahaya Bello ti ṣe Okene.
Gomina naa ati iyawo rẹ na si ti tẹka.
Lẹyin to tẹka tan ni ibudo idibo rẹ to wa ni unit 11 Okene Eba Agasa Ahache ni ijọba ibilẹ Okene o sọ fawọn akọroyin pe ọkan ohun balẹ pe oun yoo jaweolubori.
Akọroyin wa jabọ pe awọn oludibo ni Unit 34 Okene paapa julọ awọn obinrin tete jade lati wa dibo ti awọn kan si ti dibo lẹyin ayẹwo to peye lati ọdọ awọn oṣiṣẹ ajọ eleto idibo to wa nibẹ.



Awọn akọni ọmọ Naijiria ti n ṣiṣẹ sin orilẹ-ede baba wọn lati kopa ninu eto idibo oni ni Bayelsa






Bó tílẹ̀ jẹ́ pé ààgo mẹ́jọ ti lù, ìdìbò ko ti i gbéra sọ láwọ́n ibùdó ìdìbò kọ̀ọ̀kan ni Lokoja






Ibudo iforukọsilẹ marun le lọgọrun un ni wọn ti ṣeto iforukọ silẹ ni Bayelsa.
Ibudo idibo 1,804 ni eto idibo ti maa waye loni ni Bayela.
oludibo 889, 308 lo ti gba kaadi idibo.
Egbẹ oṣelu marundinlaadọta lo maa kopa pẹlu awọn oludije wọn.



Awọn oṣiṣẹ eleto idibo ti gori omi lati lọ sawọn ẹkun

Ṣaaju idibo ni Kogi,ikọ BBC ba awọn ara ilu sọrọ nipa afojusun wọn lori idibo ti wọn fẹ kopa ninu rẹ.
Ẹ gbọ ohun ti wọn sọ ninu fọnran fidio to wa labẹ yi.


O ni oun n kilọ fawọn to ba n gbero lati fa wahala kankan lasiko idibo sipo gomina to m bọ lọna ni ipinlẹ Kogi ati Bayelsa.
Adamu Mohammed ni ọwọ ofin yoo mu ẹnikẹni to ba n gbiyanju lati ta tabi ra ibo gomina ni ipinlẹ mejeeji ti idibo ti m bọ lọna.

Awọn oṣiṣẹ eleto aabo ti n gbe awọn ohun eelo idibo lọ kaakiri ijọba ibilẹ mẹjo to wa ni ipinlẹ Bayelsa




Aarẹ Muhammadu Buhari naa yoo foju ri bi idibo Kogi ati Bayelsa yoo ti ṣe lọ ni ọjọ Abamẹta lẹyin to tajo de lalẹ ọjọ Eti.
Oluranlọwọ rẹ lori ọrọ ibaraẹnisọrọ lori ayelujara Bashir Ahmad lo fi aworan ati fọnran fidio ibi ti aarẹ Buhari ti balẹ nilu Abuja.
Ṣaaju ni aarẹ Buhari ti parọwa sawọn oludije ati eeyan ipinlẹ wọn yi lati dibo ni irọwọrọsẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ṣaaju idibo gomina nipinlẹ Kogi ati Bayelsa lọjọ Satide ọsẹ yii, Aarẹ Muhammadu Buhari ti kilọ fawọn oṣiṣẹ eleto aabo lati dena awọn janduku to ba fẹ ji apoti idibo gbe.
Buhari ninu atẹjade to fi sita lati ọwọ oludamọran pataki lori ọrọ iroyin, Garba Shehu, sọ fawọn oṣiṣẹ eleto aabo pe ki wọn ṣiṣẹ wọn bi iṣẹ, ki wọn rii pe awọn eeyan dibo gẹgẹ bi ẹtọ wọn.
Aarẹ ni ẹnikẹni ko gbọdọ dunkoko mọ ẹnikan tabi dena ẹnikẹni lati dibo gẹgẹ ẹtọ wọn.
Bakan naa ni aarẹ Buhari kepe awọn oludibo nipinlẹ Bayelsa ati Kogi lati ṣe jẹẹjẹ nibudo ibudo idibo, ki wọn si dibo lalaafia gẹgẹ bi ofin ti laa kalẹ.


Banki Naijiria ti wọn ti n gba awọn ohun eelo idibo ni yii

Gomina ipinlẹ Ekiti tẹlẹri Ayodele Fayose ti figbe ta ṣaaju idibo Kogi pe Gomina Yahaya Bello ko fẹ ki idibo lọ ni irọwọ rọsẹ.
Loju opo Twitter rẹ lo fi ọrọ yi si ti o si pẹlu bi wọn ti ṣe n dunkoko mọ oludije ẹgbẹ SDP Natasha Akpoti ati Gomina Seyi Makinde ti ipinlẹ Oyo ṣe afihan pe nnkan ko le rọgbọ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post