Àwọn olùwọ́de ṣe àṣekágbá ìwọ́de #EndBadGovernance nílùú Abuja

Apa ariwa orilẹede Naijiria ni iwọde 'ebi n pa wa' ti fẹsẹ mulẹ julọ pẹlu bawọn ọdọ ti tu yaya jade lati fi ẹhonu han lori bi ilu ko ti fara rọ.

Ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́

  1. Tinubu kò sọ̀rọ̀ lórí ohun tí à ń bèèrè, ìfẹ̀hónúhàn wa yóò tèsíwájú – Àwọn olùwọ́de

    Protest

    NI kete ti Aarẹ Naijiria, Bola Tinubu, pari ọrọ rẹ to ba awọn eeyan sọ laaarọ ọjọ Aiku, ọjọ kẹrin oṣu kẹjọ 2024, awọn olufẹhonuhan kan ti jade lati tako o.

    Awọn olufẹhonuhan ti wọn ko fi bẹẹ pọ niye naa kora jọ si agbegbe Gani Fawehinmi Park, l’Ọjota, ipinlẹ Eko.

    Wọn n fi orin ati ariwo sọ pe ohun ti Aarẹ sọ ko yanju iṣoro Naijiria rara ni.

    Bi wọn ṣe n kọrin ijangbara ni wọn n sọ ọ di mimọ pe gbogbo koko inira tawọn n tori rẹ ṣe iwọde ko han ninu ọrọ ti Tinubu sọ.

    Wọn fi kun un pe awọn ọrọ to n gbe oriyin fun ijọba rẹ ni Aarẹ tẹnumọ ninu ohun to ba Naijiria sọ, bẹẹ, eyi ko yanju ohun ti awọn n wi.

    Awọn agbofinro wa lagbegbe ti awọn afẹhonuhan yii ti n tako Aarẹ Tinubu, wọn tilẹ pọ ju awọn ọdọ naa lọ pẹlu.

    Ikọ alaabo naa paṣẹ fawọn to n fi ẹhonu han naa lati ma ṣe kọja inu ọgba GaniFawehinmi, wọn si pada sibẹ, wọn n kọ orin atako wọn lọ.

    Aarẹ Tinubu lo ti fi owurọ kutu ba araalu sọrọ lori ọrọ aje, owo iranwọ epo to yọ kuro, ẹyawo to ṣe fawọn akẹkọọ, ipese ohun amayedẹrun ati bẹẹ bẹẹ lọ.

  2. Ilé-iṣẹ́ ọlọ́pàá fèsì sọ́rọ̀ àjọ Amnesty tó ní àwọn ọlọ́pàá ti ṣekú pa olùwọ́de 13 káàkiri Nàìjíríà

    Awon oluwode
    Àkọlé àwòrán, Awon oluwode

    Ileeṣẹ ọlọpaa orilẹede Naijiria ti sọ pe ko si òtítọ kankan ninu ọrọ ti ajọ ajafẹtọọ Amnesty International sọ wi pe awọn ọlọpaa ti ṣeku pa oluwọde mẹtala kaakiri orilẹede Naijiria.

    Agbẹnusọ ọlọpaa, Muyiwa Adejobi ṣalaye pe afurasi bii 681 ni ọlọpaa ti mu fun ọkan o jọkan iwa ọdaran l'asiko ifẹhonuhan to ti bẹrẹ lati Ọjọbọ ọsẹ to kọja.

    Adejobi sọ pe ipinlẹ Gombe, Jigawa, Kaduna, Sokoto, Nasarawa, Katsina, Kano ati Abuja ni ile iṣẹ ọlọpaa ti mawọn afurasi odaran naa.

    Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa fikun ọrọ rẹ pe ọlọpaa kan tawọn ti ro pe o ti ku tẹlẹ ti n mi pada bayii.

    "Ọlopaa mẹsan an lo farapa lẹyin t'awọn oluwọde ṣe ikọlu si wọn.Ọkan lara wọn ti a ro pe o ti ku tẹlẹ ni o ti ye bayii.Amọ, ẹsẹ kan aye, ẹsẹ kan ọrun ni o wa," Adejobi lo sọ bẹẹ.

    Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ni awọn ọlọpaa ko pa oluwọde kankan bo tilẹ jẹ pe awọn olufẹhonuhan n ṣe nnkan to n bi awọn ọlọpaa ninu.

    O ni awọn meje to ku lasiko iwọde ko ni ohun kohun ṣe pẹlu ọlọpaa tori kii ṣe ọlọpaa lo pa wọn.

    Amnesty International tun fi ẹsun kan ọlọpaa pe wọn n lo ọgbọn lati ṣeku pa awọn eeyan nigba ti wọn ba ti ko ara wọn jọ tan, ati pe wọn tun n lo ọta ìbọn gidi pẹlu awọn oluwọde.

    Adejobi ṣalaye pe eeyan mẹrin lo ku nipinlẹ Borno lati ọwọ awọn agbesunmomi Boko Haram/ISWAP ti wọn darapọ mawọn to n ṣe ifẹhonuhan.

    Bakan naa ni o ṣalaye pe awakọ Honda kan fi ọkọ rẹ kọlu awọn oluwọde eyi to fa iku eeyan meji.

    Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa tun fikun ọrọ rẹ pe fijilante kan yinbọn pa ọkan lara awọn to no ifẹhonuhan lati jale ni Yauri, ni ijọba ibilẹ Yuari nipinlẹ Kebbi.Adejobi ni bayii ni ọrọ awọn meje to ku lasiko ifẹhonuhan ṣe jẹ.

  3. Ìpínlẹ̀ Borno f’òpin sí òfin kónílé-ó-gbélé

    Gomina Zulum ti ipinlẹ Borno

    Lẹyin ti ado oloro kan bu gbamu lagbegbe Kawori, ipinlẹ Borno, ti eeyan mẹrindinlogun si di oloogbe, Gomina ipinlẹ naa, Babagana Umar Zulum, ti fopin si ofin konile-o-gbele to wa ni Borno.

    Nigba to n sọrọ, Gomina Zulum ba ẹbi awọn to ku ninu ibugbamu naa kẹdun.

    Bakan naa lo tọrọ alaafia fun awọn eeyan to fara kaasa ado oloro yii, ṣugbọn ti wọn ko ku, ti wọn ṣi n gba itọju nileewosan.

    Gomina Zulum ṣalaye pe nitori awọn Boko Haram to n da ipinlẹ Borno laamu loun ṣe ṣofin naa tẹlẹ.

    O ni ki wọn ma baa gba ibi iwọde wọle loun ṣe ṣofin konile-o-gbele.

    Zulum fi kun un pe awọn ọbayejẹ ẹda darapọ mọ awọn to n wọde wọọrọwọ, wọn gbiyanju lati da rogbodiyan silẹ, o ni ṣugbọn awọn agbofinro kapa wọn.

    Nigba to n kede opin konile-o-gbele naa, Gomina Zulum sọ pe kawọn eeyan maa ba iṣẹ oojọ wọn lọ laifoya.

    O ni awọn agbofinro yoo ṣi tẹsiwaju lati maa ṣo Borno, ki wọn le koju ohunkohun to ba tun fẹẹ fa wahala kankan.

  4. Àwa olórí ni ìṣóro ẹkùn Àríwá Nàìjíríà - Gomina ipinlẹ Kaduna

    Gomina ipinlẹ KAduna

    Bi ifẹhonuhan nipa ebi to n pa araalu ṣe wọ ọjọ kẹta lorilẹde Naijiria, Gomina ipinlẹ Kaduna, Shehu Sani,ti sọ pe iṣoro to n koju apa Ariwa orilẹede yii ko ṣẹyin awọn olori wọn.

    Gomina Sani sọrọ yii fun BBC lasiko to n ṣalaye nipa iwọde to n lọ lọwọ ọhun, eyi ti Kaduna naa jẹ ọkan lara awọn ibi ti rogbodiyan ti bẹ silẹ.

    Gẹgẹ bo ṣe wi, ’’ loootọ ni awọn to n fi ẹhonu han ni ẹtọ lati ṣe bẹẹ labẹ ofin, ṣugbọn bi a ko ba ni i parọ funra wa, pupọ ninu awọn to jẹ ki ifẹhonuhan yii waye ni wọn ti di ipo agbara mu ri nigba kan, ṣugbọn wọn kuna lati tun igbesi aye awọn eeyan ṣe.

    ’’ Asiko ti to bayii fun awa olori lapa Ariwa Naijiria, lati ba ara wa sọ otitọ ọrọ, ka si bẹru Ọlọun Allah.’’

    Gomina Sani sọ pe ko ti i pẹ ju fun awọn olori lapa Oke-Ọya lati dide kuro ninu ìṣẹ́ ati òṣi to n ba awọn eeyan agbegbe naa finra.

    O ni ki awọn araalu paapaa ti wọn jẹ ọmọ Ariwa dide, ki wọn gba ara wọn lọwọ aito- imọ ati oju dudu to lu abala Naijiria yii pa.

    Eyi ni yoo mu nnkan yatọ si bo ṣe wa lati ọdun gbọọrọ bi Gomina Sani ṣe sọ.

  5. Ìgboro ìlú Kano dá páropáro nítorí ìséde tí ìjọba kéde lẹ́yìn tí rògbòdìyàn wọ ìwọ́de níbẹ̀

    Aworan bi igboro ṣe da ní ilu Kano nitori konile o gbele.

    Paroparo ni awọn oju popo da nipinlẹ Kano latigba ti Gomina Abba Yusuf ti kede ofin konile-o-gbele, latari iwọde to di rogbodiyan nipinlẹ naa.

    Aworan bi igboro ṣe da ní ilu Kano nitori konile o gbele.

    Aṣoju ikọ iroyin BBC ni Kano, ṣalaye pe ko si mọto ni titi, bẹẹ ni awọn eeyan perete ni wọn n fẹsẹ rin lẹsẹkuku, ti ko jinna si ile wọn.

    Aworan bi igboro ṣe da ní ilu Kano nitori konile o gbele.

    Awọn eeyan ti wọn tun n jokoo ni meji-mẹta leeyan tun le ri ni Kano bayii gẹgẹ bi iwadii BBC.

    Iwaju ile kaluku wọn si ni wọn n jokoo si, ti wọn n takurọsọ.

    Aworan bi igboro ṣe da ní ilu Kano nitori konile o gbele.

    Ko si ọja tita yanturu ti gbogbo aye mọ ni iṣẹ wọn ni Kano, awọn agbofinro ti ijọba da sita ni wọn n lọ kaakiri.

    Aworan bi igboro ṣe da ní ilu Kano nitori konile o gbele.

    Tẹ o ba gbagbe, ọjọ akọkọ ti iwọde ebi n pa wa bẹrẹ ni wahala bẹ silẹ ni Kano. Oku sun, wọn ba dukia jẹ, wọn si sọ iwọde naa di ọna lati jale pẹlu.

    Rogbodiyan naa lo mu Gomina Abba Yusuf kede ofin konile-o-gbele, titi ti alaafia yoo fi jọba.

  6. Fídíò bí àwọn agbófinró ṣe fe fi tajútajú tú àwọn olúwọ́de ká nílùú Abuja

    Àkọlé fídíò, Fidio iwọde nilu Abuja lọjọ Ẹti
  7. Àwọn olùwọ́de tó jẹ́ Mùsùlùmí ń k'írun níbi ìwọ́de lọ́jọ́ Ẹtì, Àwọn olùwọ́de tó jẹ́ Mùsùlùmí ń k'írun níbi ìwọ́de lọ́jọ́ Ẹtì

    Awọn oluwọde  kan pẹlu aṣia Naijiria nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde kan pẹlu aṣia Naijiria nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Awọn oluwọde  kan n kirun Jumat nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde kan n kirun Jumat nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Awọn oluwọde  kan nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde kan nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Awọn oluwọde nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Awọn oluwọde  kan n kirun Jumat nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde kan n kirun Jumat nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Awọn oluwọde gbe patako alakọle dani nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde gbe patako alakọle dani nibi iwọde ni agbegbe Ọjọta niluu Eko lọjọ Ẹti.
  8. Wo fídíò bí ìwọ́de ṣe lọ sí l'Ọ́jọ́bọ̀

    Àkọlé fídíò, Wo fídíò bí ìwọ́de ṣe lọ nílùú Ibadan l'Ọ́jọ́bọ̀
  9. “Ogún èèyàn ló kú lásìkò ìwọ́de ọjọ kan ni Naijiria’ - Àbọ̀ ìwádìí kan

    Aworan iwọde kan

    Ko din ni ogun eeyan ti wọn di oloogbe ninu iwọde to bẹrẹ ni Naijiria lọjọ akọkọ ninu oṣu kẹjọ ọdun 2024, ipinlẹ mẹfa ni iṣẹlẹ iku naa si kan.

    Ileeṣẹ kan, Beacon Consulting, to n tọpinpin eto aabo, lo fidi iwadii wọn mulẹ bayii lori iwọde to n kede pe opin gbọdọ ba iṣakoso buruku ni Naijiria.

    Gẹgẹ bi abajade iwadii ileeṣẹ yii, wọn ni ipinlẹ mẹwaa ni rogbodiyan ti bẹ silẹ lasiko iwọde.

    Awọn ipinlẹ naa ni: Adamawa, Borno, Gombe, Jigawa, Kaduna, Kano, Kebbi, Nasarawa, Niger ati Yobe.

    Ileeṣẹ yii ṣalaye pe eeyan mẹfa ni wọn pa nipinlẹ Niger, mẹrin ku ni Borno, eeyan mẹta si dero ọrun ni Kaduna.

    Beacon Consultant sọ pe eeyan mẹrin lo ba iwọde lọ ni Kano, ẹnikan lo ba a lọ ni Kebbi, awọn meji si dero ọrun ni Jigawa.

    Iwadii wọn naa tun sọ pe awọn agbofinro kuna lati ṣiṣẹ wọn, eyi ni wọn lo fa a ti iwọde fi di rogbodiyan.

    Ijọba orilẹede yii ko ti i fi atẹjade to n tọka iye eeyan to ku sita lori rogbodiyan naa.

  10. Ẹ fòpin sí ìwọ́de tó ń dúnkoòkò mọ́ àwọn èèyàn yíí-Igbìmọ̀ àwọn olórí ẹ̀sìn ní Nàìjíríà pàrọwà

    Igbimọ olori awọn ẹka ẹsin ni Naijiria

    Oríṣun àwòrán, nirec

    Ẹgbẹ awọn olori ẹsin lorilẹede Naijiria, iyẹn Christian Association Of Nigeria (CAN) ati Nigerian Supreme Council of Islamic Affairs (NSCIA), ti rọ awọn olufẹhonuhan lati da iwọde naa duro.

    Arcbishop Daniel Okoh, Alaga CAN ati Alaaji Muhammad Sa'adu Abubakar (III) ni wọn pe ipe yii nibi ipade awọn olori ẹsin mejeeji to waye lọjọ Ẹti, ọjọ keji, oṣu kẹjọ ọdun 2024 yii.

    Bakan naa ni Akọwe apapọ ajọ Nigeria Inter-Religious Council (NIREC), Ọjọgbọn Cornelius Afebu Omonokhua, wa nibi ipade ọhun.

    Ninu atẹjade ti wọn fi sita lẹyin ipade ni awọn olori ẹsin mejeeji ti ṣalaye pe òfò nla lo ṣe orilẹede yii laarin wakati perete ti iwọde naa fi waye.

    Awọn ajọ mejeeji so pe awọn mọ pe oju awọn eeyan n ri mabo lorilẹede yii loootọ, wọn ni ṣugbọn jagidijagan kọ ni ọna abayọ.

    Wọn fi kun un pe iwọde to n dunkooko mọ ẹmi awọn eeyan lo n lọ lọwọ yii, yoo si tun ba nnkan jẹ si i ni.

    NIREC to n ri si ọrọ ẹsin ni Naijiria, rọ awọn oluwọde lati dawọ rẹ duro, wọn ni ki wọn jẹ ki ijọba wa ojutuu si iṣoro naa funra wọn.

    Bakan naa ni ajọ yii ni ki ijọba pẹlu tete gbe awọn igbesẹ ti yoo fi ọkan ara ilu balẹ, ti yoo si dahun si ẹbẹ wọn.

  11. Ìwọ́de ti bẹ̀rẹ̀ fún ọjọ́ kejì nílùú Abúja

    Àwọn oluwọde tun ti korajọpọ si Berger nílùú Abuja furniture ètò iwode lonii to jẹ ọjọ́ keji osu kẹjọ yii.

    Iroyin sọ pe agbegbe Berger nilu Abuja ni wọn korijọ si ki awọn agbofinro atawọn ṣọja to wa ni ikalẹ fun amojuto eto abo to bẹrẹ si ni yin tajutaju si wọn.

    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja
    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja
    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja
    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja
    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja

    Ikọ ọlọpaa ati ọmọ ogun orilẹede Naijiria tun kọlu awọn oluwọde ni Berger niluu Abuja, ti wọn si bẹrẹ si n yin afẹfẹ gaasi tajutaju ati ibon lati fi tun wọn ka.

    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja
    Awọn oluwọde niluu Abuja
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde niluu Abuja
  12. Àwọn agbófinró ti ṣàwárí Sẹ́nétọ̀ tó ń ṣe agbódegbà fáwọn olùwọ́de - Nyesom Wike

    Awọn agbofinro n wo awọn oluwọde lọọkan

    Minisita fun olu ilu Naijiria, Nyesom Wike ti ṣalaye pe oju awọn agbofinro ti mọlẹ si ara Sẹnetọ kan fun jijẹ agbodegba fun iwọde to waye ni ilu Abuja tii ṣe olu ilu Naijiria.

    Lasiko to fi n ba awọn akọroyin ọrọ lẹyin ipade eto abo to waye ni Minisita Wike sọ eyi.

    Wike ni minisita ti wọn n tka si naa, vbi o tilẹ jẹ pe ko darukọ rẹ, lo n pin ounjẹ fun awọn oluwọde.

    O ni nigba to ba ya, awọn agbofinro yoo ran’sẹ pe sẹnetọ naa.

    Bakan naa lo tun ki awọn oluwọde nilọ pe ile ẹjọ ti gbe idajọ kalẹ pe wọn ko gbọdọ kọja papa iṣire MKO Abiọla fun iwde wọn, nitori naa ki wọn tẹle ofin naa lo dara.

  13. Gómìnà Aiyedatiwa kan sáárá sáwọn èèyàn Ondo bí wọn kò ṣe darapọ̀ mọ́ ìwọ́de

    Gomina Lucky Aiyedatiwa

    Oríṣun àwòrán, Lucky Aiyedatiwa/FACEBOOK

    Gómìnà ìpínlẹ̀ Ondo, Lucky Aiyedatiwa ti kan sáárá sáwọn èèyàn ìpínlẹ̀ náà fún bí wọ́n ṣe kọ̀ láti kópa ìwọ́de tó wáyé láwọn ìpínlẹ̀ mìíràn káàkiri Nàìjíríà.

    Dípò ìwọ́de tó wáyé láwọn ìpínlẹ̀ káàkiri, níṣe ni àwọn èèyàn ìpínlẹ̀ Ondo bá iṣẹ́ ajé wọn láì fa wàhálà tàbí ìwọ́de kankan.

    Agbẹnusọ gómìnà Aiyedatiwa, Ebenezer Adeniyan nínú àtẹ̀jáde kan tó fi sójú òpó Facebook rẹ̀ ní gómìnà Aiyedatiwa ní ó fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ìpínlẹ̀ Ondo àtàwọn èèyàn rẹ̀ fẹ́ràn àláfíà àti pé ó wà lára àwọn ìpínlẹ̀ tí àláfíà ti ń jọba jùlọ lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

    Aiyedatiwa wá dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn èèyàn ìpínlẹ̀ náà fún bí wọ́n ṣe gbọ́ ìkìlọ̀ láti má kópa nínú ìwọ́de náà.

    Gómìnà náà fi kun ọ̀rọ̀ pé òun mọ nǹkan tí àwọn èèyàn ń kojú látàrí ètò ọrọ̀ ajé Nàìjíríà tó ti dẹnu kọlẹ̀ tó sì ṣèlérí pé ìṣèjọba òun máa ri dájú láti wá ojútùú sáwọn ìṣòro táwọn èèyàn ń kojú ní ìpínlẹ̀ náà.

    Ó ní láìpẹ́ yìí ni àwọn yóò bẹ̀rẹ̀ sí ní gbé àwọn ètò àti àkànṣe iṣẹ́ láti mú ìdẹ̀kùn bá àwọn ará ìlú jáde.

  14. Ìjọba Kano kéde kónílé-ó-gbélé lẹ́yìn tí wàhálà bẹ́ sílẹ̀ níbi ìwọ́de

    Àwọn olùwọ́de

    Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano, Abba Kabir Yusuf kéde òfin kónílé-ó-gbélé ní ìpínlẹ̀ náà fún wákàtí mẹ́rìnlélógún.

    Ìkéde yìí ló wáyé lẹ́yìn tí ìwọ́de tó wáyé ní ìpínlẹ̀ náà di wàhálà.

    Ìròyìn sọ pé àwọn èèyàn dágbére fáyé níbi ìwọ́de náà nígbà tí àwọn olùwọ́de ṣ ìkọlù sí ilé ìjọba àmọ́ BBC kò ì tíì fìdí èyí múlẹ̀.

    Gómìnà Yusuf wá pa á láṣẹ́ fáwọn agbófinrọ láti ri dájú pé òfin kónílé-ó-gbélé náà fẹsẹ̀ múlẹ̀.

  15. Ìjọba kéde kónílé-ó-gbélé lẹ́yìn tí ìbúgbàmù ṣekúpa èèyàn 16

    Àwọn olùwọ́de ní Kano

    Gómìnà ìpínlẹ̀ Borno, Babagana Umar Zulum ti kéde òfin kónílé-ó-gbélé ní ìpínlẹ̀ náà láti dáàbò bo ẹ̀mí àti dúkìá àwọn èèyàn.

    Wákàtí mẹ́rìnlélógún ni òfin kónílé-ó-gbélé náà yóò fi wáyé.

    Àtẹ̀jáde kan tí agbẹnusọ iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Borno, Nahum Kenneth Daso ní lẹ́yìn tí gómìnà Zulum ṣèpàdé pẹ̀lú àwọn olórí ẹ̀ṣọ́ ààbò ní ìpínlẹ̀ náà ni wọ́n fẹnukò láti gbé ìgbésẹ̀ náà.

    Agbẹnusọ ọlọ́pàá náà ní ojúṣe iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíríà ni láti láti ri pé ààbò wà fún gbogbo èèyàn lẹ́yìn ìṣẹ̀lẹ̀ ìbúgbàmù tó wáyé ní Kawori.

    Èèyàn mẹ́rìndínlógún (16) ló pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìbúgbàmù náà tí ọ̀pọ̀ àwọn mìíràn sì farapa yánnayànna.

    Daso ní àwọn tó farapa náà ló ti wà ní ilé ìwòsàn níbi tí wọ́n ti ń gba ìtajú.

    Ó wá rọ àwọn èèyàn ìpínlẹ̀ Borno láti wà ní pẹ̀lẹ́ kùtù, kí wọ́n sì ri d;ajú pé àwọn kò ṣe nǹkan tó lòdì sófin.

  16. Agbófinró rọ tajútajú sí àwọn olùwọ́de ní Abuja

    Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Àkọlé àwòrán, Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Àkọlé àwòrán, Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Àkọlé àwòrán, Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Àkọlé àwòrán, Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
    Àkọlé àwòrán, Agbofinro yin tajutaju l’Abuja
  17. "Ẹ ba wa kó ṣọ́jà púpọ̀ síì wá sí Zamfara"

    Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara

    Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara ni eto abo to duro deede lawọn n beere fun.

    Awọn olugbe Zamfara naa jade lati fi ẹhonu wọn han lori ‘iwọde-ebi-n-panu’ to n waye jakejado Naijiria.

    Awọn oluwọde naa rọ ijọba lati pese abo to peye fun wọn ni ipinlẹ naaki wọn si tun fi kun iye awọnṣọja ti wọn n ko ranṣẹ si ipinlẹ naa.

    Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
    Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
    Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
    Àkọlé àwòrán, Awọn oluwọde ni ipinlẹ Zamfara
  18. Àwọn àwòrán láti Ibadan

    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àwọn àwòrán láti Ibadan
    Àkọlé àwòrán, Àwọn àwòrán láti Ibadan
  19. Ìwọ́de fa wàhálà dání ní Kano, olùwọ́de mẹ́ta fara gbọta

    Awọn oluwọde ni KAno

    Bi iwọde ṣe n waye kaakiri orilẹede Naijiria lati fi ẹhonu wọn han si bi nnkan ṣe le gogo lorilẹede naa, ogunlọgọ awọn ọdọ lo jade ni ilu Kano ti wọn si n korajọ pọ si iwaju ile ijọba ipinlẹ naa ni ilu Kano.

    Akọroyin BBC to wa ni Kano jabọ pe oniruru patako alakọle ni awọn ọdọ naa ko lọwọ ti wọn si n sọ awọn ọrọ ẹhonu loriṣiriṣi.

    Gẹgẹ bi o ṣe ọ, o ni nnkan bii eeyan mẹta lo ti fara gbọta ibọn lara awọn oluwọde naa.

    Awọn oluwọde ni KAno
    Awọn oluwọde ni KAno
    Awọn oluwọde ni KAno
  20. Ìwọ́de bẹ̀rẹ̀ ní ìlú Eko, Ibadan, Portharcourt, Abuja

    Àkọlé fídíò, Ìwọ́de ní ìlú Eko

    Agbegbe Iwo road lawọn Oluwọde naa ti gbera ki wọn to kọju si idi apẹ gba agbegbe Gate lọ.

    Awọn oluwọde ti bẹrẹ iwọde nilu Eko.

    Agbegbe Ọjọta ni wọn kọkọ fi ipade si. Orin ẹhonu, pẹlu patako alakọle loriṣiriṣi ni wọn n gbe jade lati fi ẹhonu wọn han.

    Àkọlé fídíò, Ìwọ́de ní ìlú Eko