Àwọn akọrin ìjọ CAC gba ìtúsílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ajínigbe ní ìpínlẹ̀ Ondo

Awọn akọrin ijọ CAC Oke-Igan nilu Akure nipinlẹ Ondo to ku sọdọ awọn ajinigbe lo ti gba itusilẹ.
Awọn ajinigbe ji awọn akọrin naa gbe lagbegbe Ẹlẹgbẹka nijọba ibilẹ Ọsẹ lọjọ Ẹti to kọja.
Ibi isinku obi aluduru ijọ naa ni wọn n lọ ki awọn agbebọn o too dawọn lọna ti wọn si ko awọn mọkandinlogun to wa ninu ọkọ ijọ naa lọ.
Ẹwẹ, mẹjọ ninu wọn moribọ loru ọjọ naa mọju to si ku awọn mọkanla.
Owurọ ọjọ Abamẹta lawọn ajinigbe naa pe alufaa ijọ, Benjamin Akanmu, lati beere fun aadọta miliọnu naira owo idande.
Lati ọjọ naa ni awọn agbofinro ti bẹrẹ iṣẹ takuntakun lati le doola ẹmi awọn mọkanla naa.
Ni nkan bii aago mọkanla alẹ Ọjọbọ ni iroyin jade pe awọn ajinigbe ọun ti tu awọn mọkanla naa silẹ, ti wọn si pada de ijọ wọn nilu Akure ni nkan bii aago mejila oru.
Alufaa Akanmu ṣalaye fun BBC News Yoruba wi pe awọn ajinigbe ọun lo fi awọn mọkanla to ku naa silẹ ki wọn maa lọle layọ.


























