You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
ECOWAS kéde Ààrẹ Tinubu gẹ́gẹ́ bí Alága
Published
Aarẹ orilẹede Naijiria, Bola Ahmed Tinubu ni wọn kede gẹgẹ bi alaga Ajọ ECOWAS fun gbogbo orilẹede adulawọ.
Igbesẹ yii ni wọn kede nibi ipade mẹtalelọgọta ti ajọ ọhun to waye niluu Bissau, to jẹ olu ilu orilẹede Guinea-Bissau.
"A mu ijọba awarawa lọkunkundun, ijọba awarawa lo le pupọ sugbọn o le di ijọba mu." eyi ni ọrọ Aarẹ Tinubu lẹyin to tẹwọgba iwe ipo naa lọwọ alaga to kogba wọlẹ, iyin Aarẹ Guinea Bissau, Umaro Embalo.
Ipo alaga ECOWAS lo jẹ ipo kan ti awọn olori orilẹede to wa ninu ajọ ọhun ma dimu fun ọdun kan.
Aarẹ tẹlẹ lorilẹede Naijria, Muhammadu Buhari lo di ipo naa mu ni ọdun 2018 si 2019.