Jacob Zuma: Iléẹjọ́ tó gá jùlọ ní South Africa sọ̀ aarẹ́ àná sẹ́wọ̀n oṣù mẹ́ẹ̀dógún

Oríṣun àwòrán, AFP
Ile ẹjọ to ga julọ lorilẹede South Africa ti sọ aarẹ ana lorilẹede Naa, Jacob Zuma si ẹwọn ọdun kan ati osu mẹta.
Ileejẹ to ga julọ ni South Africa naa gbe igbesẹ yii lẹyin ti wọn ti se igbẹjọ aarẹ ana naa, ti wọn si ni o jẹbi ẹsun titẹ asẹ ileejọ loju.
Wọn ni Jacob Zuma fi aake kọri lati yọju siwaju igbimọ olugbẹjọ kan to n tanna wadi ẹsun iwa ajẹbanu ti wọn fi kan nigba to wa nipo aarẹ orilẹede naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Orí àgbá ẹ̀tù láwọn èèyàn Ibarapa jókòó lé, wàhálà ń bọ̀ - OPC mẹ́ta tó gba ìdáǹdè
- Jide Kosoko, tí mo bá tú àṣírí rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ yóò dọwọ́ bojú - Nkechi Blessing yarí
- Mo dẹ́kun àdúrà gbígbà lẹ́yìn ikú Ajimobi - Florence aya olóògbé
- Oríire dé! Aláànú kan fún Kemisola ní ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ dé fásitì
- Omo Borty sọ̀rọ̀ sókè lórí ìbáṣepọ̀ rẹ̀ àti Dino Melaye
- Òǹyẹ̀ kò lè yẹ ìwọ́de Yoruba Nation l‘Eko, mò ń bọ̀ níbẹ̀ - Sunday Igboho
- Obasanjo fèsì lórí báwọn ọmọ Nàìjíríà kan ṣe ń pe ààrẹ Buhari ní Jubril ti Sudan
Ọpọ ẹsun ajẹbanu ni wọn we mọ Zuma lọrun lasiko to wa lori oye, eyi to pari ọdun 2018.
Iroyin kan ni awọn olokoowo nla nla atawọn eekan oloselu lo pawọpọ ditẹ papọ lati tọwọ pọ eto idajọ naa.
Amọ aarẹ ana nilẹ South Afrika naa yọju lẹẹkan soso siwaju igbimọ oluwadi ọhun amọ ti ko yọju sibẹ mọ.
Igbimọ oluwadi naa, ti adajọ Raymond Zondo lewaju rẹ lo rọ ile ẹjọ to ga julọ naa lati da si ọrọ naa amọ a ko mọ boya wọn yoo lọ gbe Zuma nile.
Ninu igbẹjọ miran, Zuma ti bẹbẹ losu to kọja pe oun ko jẹbi ẹsun iwa ajẹbanu kan ti wọn fi kan ninu igbẹjọ owo to to biliọnu marun dọla to yẹ ki wọn fi ra eroja ijagun lati ọdun 1990 siwaju.

























