Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ jàǹdùkú olóṣèlú méji pẹ̀lú ìbọn
Ọwọ ọlọpaa ti ba awọn ọkunrin meji kan,Edwin Obanor ati Audu Tajudeen, nipinlẹ Edo.
Ibọn ilewọ mẹrin ni wọn ba lọwọ wọn lẹyin ti olobo ta awọn ọlọpaa pe janduku to fẹẹ da ibo ọjọ Satide oni yii ru nipinlẹ naa ni wọn.
Alukoro ọlọpaa Naijiria, ACP Olumuyiwa Adejobi, ṣalaye pe alẹ ọjọ Ẹti, ogunjọ, oṣu Kẹsan-an ọdun 2024, ni ọwọ ba Obanor, olori ẹgbẹ janduku kan, ni wọọdu kẹrin, Eredo.
Bẹẹ ni wọn mu Tajudeen ni Igara Akoko, Edo. Adejobi sọ pe wọn ti wa ni ahamọ, wọn yoo si foju wina ofin bo ṣe yẹ.