Kókó, Àwọn Janduku ti dojú àpótí ìdìbò bolẹ̀ ní Emure Ekiti
Àwọn ajo olopaa ni awọn ń wa awọn janduku ti wọn doju apoti ibo bolẹ̀ ni Ward 6 Emure Ekiti.
You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
A ń mú ètò gbogbo bó ṣe ń lọ níbi ìdìbò fún ipò gómínà káàkiri ipinlẹ Ekiti.
Olubusola Afolayan and Adedayo Owolabi
Àwọn ajo olopaa ni awọn ń wa awọn janduku ti wọn doju apoti ibo bolẹ̀ ni Ward 6 Emure Ekiti.
Oludije si ipo gomina labẹ ẹgbẹ oselu APC, John Kayode Fayemi ni eto idibo lọ ni irọwọrọsẹ, amọ O fi kun pe iroyin lati ọdọ awọn Asoju rẹ̀ fi han pe kaadi idibo wọn ko sisẹ.
Ṣẹgun Oni, gomina ipinlẹ Ekiti nigba kan ri naa ti dibo nilu rẹ̀, Ifaki Ekiti.
Ẹleka ba BBC sọrọ pe niṣe lawọn ọlọpaa n woran nigba tawọn oloṣelu n pin owo fawọn oludibo lanaa.
BBC ti kọkọ gbe fidio naa sita to ṣafihan bi awọn oludibo ṣe n sare lọ gba N4000.
O le ni ogun bọ́ọ̀si ọkọ̀ ologun to kó àwọn ọmọ ogun wọ Ado Ekiti nisiyi.
Akoroyin BBC ri wọn lopopona ọja Ọba.
Lẹyin ti ẹrọ kaadi idibo kọ ọwọ́ Eleka ni awọn ajọ INEC jẹ kó lo dibo lai lo ẹrọ kaadi idibo
A tun ti gbọ bayii pe iyawo Kayọde Fayẹmi ko lee dibo nitori ẹrọ to n yẹ ika oludibo wo naa tun kọ ika iyawo Fayẹmi gẹgẹ bo ti se fun Olusọla Ẹlẹka. Fayẹmi ati iyawo rẹ ti wa pada si ile wọn bayii.
Ki agogo mẹjọ to lù ni ilu Afao Ekiti to jẹ ilu gomina Fayoṣe lawon oludibo ati oṣiṣẹ INEC ti wa nikale lati bẹrẹ idibo, woorowo nidibo n lọ nibẹ, gomina Ayodele Fayose ko tii jade wa dibo. Awon oludibo to ba BBC sọrọ ni inú àwọn dun bi o ṣe ri yii pelu ireti pe bee ni yoo se ri de opin. Yatọ si awọn iṣẹlẹ diẹ pẹlu ẹrọ ayekawo ti ko tete ri awọn ika kan sugbon lẹyẹ o ṣoka ni awọn onimọ ẹrọ àjọ INEC ti wa ojuutu sii.
Adeniyi Adebayọ, Gomina tẹ́lẹ̀ ní ìpinlẹ Ekiti, ti sọ ni wọọdu idibo rẹ pe eto idibo naa n lọ ni pẹlẹ-putu, ti ko si si wahala kankan.
Bakan naa lo ni awọn ọlọpaa n sisẹ wọn bo ti yẹ, ti diduro wọn lawọn ibudo idibo si n se iwuri fun awọn oludibo lati jade wa.
Awọn wọnyii ni oludibo loriṣiiriṣii to ti jáde sita wa dibo kaakiri ijọba ibilẹ Ekiti
Bakan naa ni awọn oludibo kan ko lee dibo ni awọn wọọdu kan nitori pe kaadi idibo ti ọjọ ti lọ lori rẹ ni wọn mu wa si ibudo idibo.
Lara wọn ni mama ọgọrun ọdun kan, to jade wa dibo, mama Comfort Ibiyẹye Bọdunde, to jẹ pe kaadi idanimọ lo mu wa dipo kaadi idibo.
Mama agba Abọdunde wa gba awọn oloselu nimọran lati ma ṣe da rogbodiyan silẹ, amọ ki wọn jẹ ki alaafia jọba lasiko eto idibo naa.
Oludije fún ipò gomina fẹgbẹ oṣelu APC, Ọmọwe Kayọde Fayẹmi àti iyawo rẹ̀ naa ti de si ibùdó idibo wọọdu rẹ̀ lati wa dibo.
Ọpọ eeyan lo tẹle e lẹyin, to si ti se ayẹwo orukọ rẹ.
Iroyin to n tẹ wa lọwọ ni pé oludije fun ẹgbẹ oselu PDP, Ọjọgbọn Olusọla Ẹlẹka ko tii lee dibo ni wọọdu rẹ̀.
Amọ, a gbọ pe ẹrọ naa gba ika iyawo rẹ, to si ti dibo.
Lati ìdájí ni awọn eniyan ipinlẹ Ekiti ti n jade sita, ti wọn n rin lo si ibudo idibo kaakiri nipinle naa fun ayẹwo orukọ wọn lati fi dibo. O lé ni ọtale lẹgbẹrun lọna ọgọrun mẹfa (667,270) oludibo ni ti wọn ti forukọ silẹ pẹlu ajọ eleto idibo INEC lati dibo loni nipinlẹ Ekiti.
Láti ilé agódo ilé akéde BBC Yorùba la ti ń ki gbogbo ẹ̀yin olólùfẹ́ wa pe Ẹ kaabọ sórí ètò akànṣe fún ètò ìdìbò Ekiti ni Nàìjíríà. Etò yii ni a gbé kalẹ̀ fún ìgbádùn yin loni ti a o ti máa mú gbogbo nkan to n ṣẹlẹ nipinlẹ Ekiti wa fún yin. Emi Olubusọla Afọlayan ni atọ́kùn yín fún òwúrọ̀ yii. Gbogbo àwòrán, fídíò àti ifọrọwanilẹnuwo pẹlu awọn eekan ninu oṣelu lọkan kò jọkan ni a o maa mu wa.