Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo ti sọ pe oju ọna one-way ni ọkunrin ti wọn ṣeṣi yinbọn pa ọmọ rẹ niluu Ibadan lana gba ṣaaju iṣẹlẹ ọhun
Agbẹnusọ ileeṣẹ naa, Adewale Osifeso sọ pe taya ọkọ ọkunrin naa lawọn fẹ yinbọn si ko to ba ọmọ rẹ, Kehinde Alade
Lọ soju opo BBC Yoruba fun ẹkunrẹrẹ
__________
Nipinlẹ Osun
Ko din ni ẹlẹwọn mẹfa to salọ kuro lọgba ẹwọn ilu Ilesha lẹyin ti ojo nla kan rọ loru ọjọ Iṣẹgun
Agbẹnusọ ọgba ẹwọn naa, Umar Abubakar ni, awọn ti bẹrẹ iṣẹ lorii bi wọn yoo ṣe ri awọn ẹlẹwọn naa mu pada laipẹ
_________
Ọkunrin kan ti dana sun iyawo ati ọmọ rẹ nijọba ibilẹ Osisioma Ngwa, nìpínlẹ̀ Abia
Awọn ti ọro naa ṣoju wọn ni òru tí gbogbo èèyàn ti sùn ni ọkùnrin náà da epo bẹntiróòlù sílé wọn, tó sì dáná si pẹlu iyawo ati ọmọ rẹ ninu ile
Ẹsun to fi kan iyawo rẹ ni pe o doju ti oun lasiko to wa bere owo ounjẹ lọwọ oun ninu ọja
Fun ẹkurẹrẹ
























