Philosophy of Ori: Olatunji ní orí ẹni ló ń dúró ti ní lọ́jọ́ ìṣòro àti lójú ikú
Awọn baba nla wa lo maa n pa a lowe pe ori ni a ba bọ, ka fi orisa silẹ nitori ko si orisa to n gbe ni bii ori ẹni.
Wọn a tun ni orisa lo ni ọjọ kan ipọnju, ori ẹni lo ni ọjọ gbogbo.
Sugbọn fun ọpọ ọmọ ilẹ Kaarọ Oojire, o loju ẹni to mọ itumọ ori bibọ, pataki rẹ ati ba se le bọ ori wa, ti yoo fi gbe wa.
Ọna lati mọ iwulo ori bibọ lo mu BBC Yoruba kan si Babalawo kan, Efuwape Olatunji, ẹni to salaye bi a se n bọ ori ati iwulo rẹ fun ẹda kọọkan.
- Babalawo lo le mo òun ti yóò gbẹyin ọ̀sándòru
- Ọmọ Elebuibon tó jẹ́ òṣèré tíátà àti ìyá awo figbe ta lórí ìdẹ́yẹsí tó ń kojú - Oyin Elebuibon
- Wo bí afurasí ọmọ ọdún 16 àti 17 ṣe pa ọmọ ọdún 11 láti fi ṣe ètùtù ọlà
- Ọwọ NAPTIP tẹ babalawo to n fọmọ sowo
- Ewé súnko! Ọ̀wọ́ EFCC tẹ ayédèrú Babaláwo pẹ̀lú òògùn abẹnugọ̀ǹgọ̀
- Ọ̀nà tó fi le è mọ gbájúẹ̀ babaláwo - Ẹlẹ́buìbọn
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Baba awo Afuwape ni ori ni ayanmọ ati Ẹlẹda ẹni, ko si yẹ ka wa laye lai bọ.
O ni ori lo n duro ti ẹda lojoojumọ, lasiko isẹlẹ ibi ati ni ọjọ iku ẹni pẹlu.
O wa fi ẹsẹ Ifa kan tọ ọrọ rẹ lẹyin eyi to sọ pataki ori bibọ, to si tun se afihan ọna to yẹ ka gba lati maa bọ ori wa loore koore.



