Goitre Patients: Àwọn èèyàn tó ní àrùn gẹ̀gẹ̀ ní ọ̀pọ̀ ìkórira àti ìdẹ́yẹsí ní àwọn ń kojú
Published
“Ọpọ wa lo ti n gbe arun gẹgẹ yii kiri fun ọdun mẹwa, mẹẹdogun ati mẹẹdọgbọn nitori ẹru n ba wa lati se isẹ abẹ.”
Eyi ni ibẹru ti ọkan lara awọn eeyan to ni arun gẹgẹ nilu Badagry fihan fun ikọ iroyin BBC Yoruba lasiko to n ba wa sọrọ.
Awọn alarun gẹgẹ naa ni ẹrun isẹ abẹ n ba awọn lati se nitori awọn le e ku, lo mu kawọn pinnu lati mase se isẹ abẹ naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìtàn ayé Taiwo Oredein rèé, àgbà òṣèlú tó parí ayé rẹ̀ sọ́gbà ẹ̀wọ̀n
- Ìtàn ìgbé ayé Bode Thomas rèé, ó kọ́ wa láti máa kó ẹnu wa ní ìjánu
- Ṣo mọ̀ pé J.F Odunjo jẹ aṣòfin àti mínísítà nílẹ̀ yìí, yàtọ̀ sí pé ó jẹ́ òǹkọ̀wé?
- Ó pé ọdún mẹ́rìnlélàádọ̀ta tí Akintola kú, ìdí abájọ ìja rẹ̀ pẹ̀lú Awolowo rè é
- Ìtàn Gbọnka àti Timi, akọni méjì tó borí Aláàfin Ṣango
- Eji Gbadero, ọmọ Ibadan àti jayé-jayé ọmọ ónílẹ̀ ti wọn yẹgi fun l'Eko
- Lisabi Agbongbo Akala rèé, ẹni tó fi ìfẹ́, ìṣọ̀kan àti ìrẹ́pọ̀ gba ilẹ̀ Ẹ̀gbá lọ́wọ́ ìmúnisìn
- Ọba Lamidi Adeyẹmi, òṣìṣẹ́ adójútòfò àti Abẹ̀ṣẹ́kùbíòjò kó tó jọba
Koda, wọn fidi rẹ mulẹ pe agbo ni awọn n lo si arun naa, amọ fun ọpọ ọdun, bakan naa ni ọmọ se ori.
Ọpọ wọn si lo sọ nipa idojuti, idẹyẹsi ati ikorira ti wọn n koju lawujọ nitori arun gẹgẹ to n ba wọn finra.
Sugbọn pupọ wọn ti setan bayii lati lọ fun isẹ abẹ lẹyin ti wọn ri awọn eeyan to se isẹ abẹ arun gẹgẹ nipinlẹ Eko, ti iku ko si pa wọn.