Kàkà k'éku mọ́ jẹ sèsé...àwọn jàndùkú dojú àpótí ìbò bolẹ̀ ní Lokoja
Ọrọ di bo o lọ o ya n mi ni ibudo idibo Madabo niluu Lokoja lẹyin tawọn ọmọ gọnfe kan da oju apoti ibo bolẹ ti ọpọ si fẹsẹ fẹ.
You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ẹ kaabọ si oju opo BBC Yoruba, wọnyi ni ohun ti awọn akoroyin wa to ti kalẹ kaakiri Naijiria n jabọ nipa ipalẹmọ idibo Aarẹ Naijiria.
Ahmed Ambali and Busayo Akogun
Ọrọ di bo o lọ o ya n mi ni ibudo idibo Madabo niluu Lokoja lẹyin tawọn ọmọ gọnfe kan da oju apoti ibo bolẹ ti ọpọ si fẹsẹ fẹ.
Ọrọ di bo o lọ o ya n mi ni ibudo idibo Madabo niluu Lokoja lẹyin tawọn ọmọ gọnfe kan da oju apoti ibo bolẹ ti ọpọ si fẹsẹ fẹ.
Adajọ Abdul Aboki (Abuja Div.),
Adajọ Joseph Ikyegh (Benin Div.),
Adajọ Samuel Oseji (Lagos Div.)
Adajọ Peter Ige (Abuja Div.)
AdajọMohammed Garba
Oni loni n jẹ ẹni a bẹ lọwẹ laarin Atiku Abubakar ti ẹgbẹ oṣelu PDP ati Muhammadu Buhari ti ẹgbẹ oṣelu APC
Nibi ni a o fi adagba eto rọ si laṣalẹ oni
Lorukọ gbogbo awọn akẹgbẹ mi ti ati jọ ṣe akojọpọ iroyin wọn yi fun yin, a n ki yin pe ẹseun fun aduroti yin. E kan si wa lawọn ojuopo wa www.bbc.com/yoruba fun ẹkunrẹrẹ iroyin miran
Ọdun nikan kọ lo n gbe awọn ọmọ orilẹede Naijiria lọ si ilu wọn.
Nitori idibo ọjọ satide, awọn olugbe ilu Abẹokuta kan pẹlu ti tẹkọleti lọ silu wọn lati lọ dibo
Ibudo idibo gomina ipinlẹ Ogun, Ibikunle Amosun ni yii.
Adugbo Itoko nilu Abẹokuta ni ibudo idibo naa wa.
Komisona ọlọpaa mẹta ni yoo maa ṣe amojuto eto idibo ni Ipinle Ekiti.
Amba Asuquo to jẹ komisona to n ṣakoso ipinle naa tẹlẹ, ati komisona mejì mii ti ọkan lara wọn jẹ Posi Ajuwon ti yoo maa ṣe amojuto agbegbe Ikere ati akegbe rẹ ti yoo maa moju to agbegbe Ido osi.
Alukoro ile iṣe olopaa ipinle Ekiti Ogbeni Ikechukwu lọ fidi oro naa mulẹ fun BBC.
Oju gbogbo yoo wa lara ipinlẹ Ọyọ lasiko idibo ọjọ abamẹta, ṣugbọn ileeṣẹ ọlọpaa ti sọ pe ko si ifoya nitori awọn ọlọpaa ti gbaradi pẹlu awọn ọlọpaa to wọ aṣọ atawọn ọtẹlẹmuyẹ.
Nibi yii ni aarẹ orilẹede Naijiria tẹlẹ, Oluṣẹgun Ọbasanjọ yoo ti dibo ni ọjọ abamẹta.
Agbo ile olushomi ni Shokori, ni ilu Abẹokuta ni orukọ ibẹ.
Ẹyin naa lee fi orukọ ibudo tiyin naa sọwọ si oju opo facebook wa ni bbcnewsyoruba
Gomina ana nipinlẹ Ekiti, Ayọdele Fayose ṣalaye fun BBC News Yoruba pe akoko to fun awọn oludibo lati mọ pe awọn ni agbara ju oloṣelu kankan lọ.
O ni aṣiṣe ni fun awọn olori lati maa ro pe ọdẹ ni araalu.
Bakan naa lo sọrọ lori ọrọ apilẹkọ ti aarẹ ba awọn ọmọ Naijiria sọ ni ọjọbọ
��
Minisita fọrọ abẹle, Abdulrahaman Dambazau, to kede ọrọ yii ni igbesẹ naa wa lati rii pe ko si wọle wọde awọn ajoji to lee fẹ wa dibo tabi da wahala silẹ lasiko idibo naa.
Bakan naam, ileeṣẹ ọlọpaa ti fofin de igbokegbodo ọkọ ni ọjọ abamẹta laaarin agogo mẹfa owurọ si mẹfa irọlẹ.
Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa, Frank Mba ni Ọga agba ọlọpaa lorilẹede Naijiria, Mohammed Adamu pa aṣẹ yii lati dena awọn janduku to lee fẹ ji apoti ibo gbe.
Fọ-fọ-fọ ni awọn ọja kun ni ilu Akurẹ nibi ti awọn eeyan ti n ra ohun jijẹ silẹ ṣaaju idibo ọjọ abamẹta.
Akroyin BBC News to wa si Oja oba ni ilu Akurẹ ṣalaye pe awọn wa lati ri wi pe awon ra ounje si ile saaju idibo to n bo lọjọ abamẹta.
Bakan naa ni awon ọlọja lọja naa pẹlu pe fun alaafia lasiko idibo ati leyin idibo.
Ariyanjiyan loriṣiriṣi lo ti n waye baye laarin awọn to fẹ ṣiṣẹ alamojuto idibo nipinlẹ Kwara.
Ohun ti wọn sọ fun BBC News Yoruba ni pe lẹyin idanilẹkọ ọjọ mẹta, orukọ awọn ti ajọ INEC gbe sita n mu ifunra lọwọ.
Ajọ EFCC ti sọ pe ijiya n bẹ fun ẹnikẹni ti ọwọ ba ba ti o n ta ibo tabi ra ibo lasiko idibo ọjọ abamẹta.
Ajọ naa tilẹ ti gbe nọmba ibanisọrọ ti awọn araalu lee pe si ti wọn ba kẹẹfin ẹnikẹni ti o ba n ta ibo tabi ra ibo.
Awọn nọmba naa niyi:
Lati Eko de Kwara, Maiduguri de Rivers ni awọn ọmọ Naijiria ti n sọ ero wọn lori ohun ti wọn fẹ nipasẹ idibo apapọ ọdun 2019.
Lẹyin orẹyin ajọ eleto idibo Inec nipinlẹ Ekiti ti bẹrẹ si ni pin awọn nnkan elo idibo ni ilu Ado Ekiti.
Nigba ti akọroyin wa de ibudo ile ifowopamọ agba, niṣe ni wọn ti n ko awọn nnkan elo naa ti wọn si ti n yanju wọn saaju pinpin wọn lọ si agbegbe ibi ti wọn yoo ti lo wọn
Ọọni ile ifẹ, Adeyẹye Ogunwusi ti rọ awọn ọmọ Naijiria lati jade lọ dibo ni ọjọ abamẹta.
Ninu ọrọ ti Ọbalaye naa fi sita ni Ile Oodua tii ṣe aafin rẹ ni Ile Ifẹ, o ni bi awọn ọmọ Naijiria, paapaajulọ awọn ọdọ ṣe tu yaya lọ ṣe ayajọ ololufẹ ni ki wọn mu irufẹ ifẹ bẹẹ dani lọ si ibudo idibo lai fa wahala.
O ni ẹbun ifẹ ti awọn ọmọ orilẹede Naijiria lee fun orilẹede yii ni lati yan awọn olori ti yoo mu idagbasoke ba orilẹede Naijiria sipo