You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ilé wó lu Bisi, ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ kú, wọ́n gé ẹsẹ̀ rẹ̀ tó ń jẹrà, inú ìrora ló wà ṣùgbọ́n Dókítà tún ń sọ pé...
Awọn agba bọ wọn ni bi a ba n wa ohun ti a o jẹ, ki a maa pade ohun ti yoo jẹ wa.
Ọrọ Abilekọ Bisi Ajayi jẹ eyi ti yoo gbomi loju ọpọlọpọ.
Bisi, jẹ oniṣowo kekeke to si jẹ wi pe inu ere to n ri lori owo rẹ yii lo fi n gbọ bukata ẹbi rẹ; iyẹn ohun, ọkọ ati ọmọ mẹrin ti wọn bi.
Amọṣa, lati nnkan bi oṣu meji bayii ni Bisi ti wa nile iwosan nibi ti ko le rin, koda ko lee yi ara pada funrarẹ lori ibusun to wa.
- A fẹ́ ta ọjà wa ló mú kí fíìmù oníhòhò ó pọ̀ lórí igbá - Rose Odika
- Ó di ìgbà tí àwọn olóṣèlú bá n fi nkan àbáláyé búra kí Naijiria tó le rójú - Ọba Ogboni Iwasẹ
- Ọ̀rọ̀ òpònú tí kò mú ọgbọ́n wa ni pé kí ọmọ Yorùbá du ipò tàbí di ààrẹ ní 2023 - Ẹgbẹ́ Àgbà Yorùbá
- Ẹ̀nìkan sọ fún mi pé iṣẹ́ ìdọ̀tí ni màá ṣe láti là, ni mo ṣe ń ta ìwé lójú pópó - Wikipedia
- Mo tọrọ ikú pẹ̀lú májèlé torí wàhálà ọkọ́ àmọ́ Ọlọ́run kò fún mi - Onírú tí kò ríran
Nigba to n ṣalaye bi irinajo aye rẹ ṣe jẹ, Abilekọ Bisi Ajayi ni oun jade gẹgẹ bi iṣe rẹ lati wa ohun ti oun atawọn ọmọ oun yoo jẹ ni ọjọ kẹfa oṣu kẹfa ọdun 2021 ni ile kan fi wo lu oun ati ọmọ ti oun pọn si ẹyin, loju ẹsẹ ni ọmọ to pọn jade laye ti wọn si gbe oun tikalara digbadigba lọ si ato egungun lọna ti ibilẹ fun itọju.
Amọṣa, o ni lẹyin asiko diẹ ni ẹsẹ naa bẹrẹ si nii run ti wọn si ni lati gee nileewosan.
Nigba ti o ṣi n ba iyipada ọtun to de ba aye rẹ yii finra ni wọn ba tun sọ fun un pe nnkan ti ṣe egungun ẹyin rẹ ati pe o nilo iṣẹ abẹ fun atunto rẹ.
- Ijà inú ẹgbẹ́ náà kò sẹ̀yìn ìbò 2023, kìí ṣe nǹkan bàbàrà - Kola Ologbondiyan
- "Èmi ni obìnrin kan ṣoṣo tó ń tún AC mọ́tò ṣe n‘Ibadan, ọ̀pọ̀ ọkùnrin ló ń wá mi wá torí mo jẹ́ olóòótọ́"
- "Mo fẹ́rẹ̀ ra ‘Sperm’ láti dá ọmọ bí torí n kò lọ́kọ títí di ẹni ọdún 47"
- Àlàyé rèé lórí ìdí tí Sunday Igboho fi ń ṣe ẹjọ́ ní Benin - Femi Falana